Nọmba 31 BM

Wọ́n Dojú Ogun Mímọ́ kọ Midiani

1 OLUWA sọ fún Mose pé,

2 “Fìyà jẹ àwọn ará Midiani fún ohun tí wọ́n ṣe sí àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn náà, o óo kú.”

3 Mose bá sọ fún àwọn eniyan náà pé, “Ẹ múra ogun kí á lè gbógun ti àwọn ará Midiani, kí á sì fìyà jẹ wọ́n fún ohun tí wọ́n ṣe sí OLUWA.

4 Ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan yóo mú ẹgbẹrun eniyan wá fún ogun náà.”

5 Nítorí náà láàrin ẹgbẹẹgbẹrun àwọn ọmọ Israẹli, ẹgbaafa (12,000) ọkunrin ni wọ́n dájọ láti lọ sójú ogun, ẹgbẹẹgbẹrun láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.

6 Mose sì rán wọn lọ sójú ogun lábẹ́ àṣẹ Finehasi ọmọ Eleasari alufaa, pẹlu àwọn ohun èlò mímọ́ ati fèrè fún ìdágìrì lọ́wọ́ rẹ̀.

7 Wọ́n gbógun ti àwọn ará Midiani gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti pàṣẹ fún Mose, wọ́n sì pa gbogbo àwọn ọkunrin wọn.

8 Wọ́n pa àwọn ọba Midiani maraarun pẹlu. Orúkọ wọn ni: Efi, Rekemu, Suri, Huri ati Reba. Wọ́n pa Balaamu ọmọ Beori pẹlu.

9 Àwọn ọmọ Israẹli kó àwọn obinrin ati àwọn ọmọ Midiani lẹ́rú. Wọ́n kó gbogbo ẹran ọ̀sìn wọn ati gbogbo agbo ẹran wọn ati gbogbo ohun ìní wọn.

10 Wọ́n fi iná sun gbogbo ìlú wọn ati àwọn abúlé wọn,

11 wọ́n kó gbogbo ìkógun: eniyan ati ẹranko.

12 Wọ́n kó wọn wá sọ́dọ̀ Mose ati Eleasari ati gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, ní òdìkejì odò Jọdani, lẹ́bàá Jẹriko.

Àwọn Ọmọ Ogun Pada Wálé

13 Mose, Eleasari ati àwọn olórí jáde lọ pàdé àwọn ọmọ ogun náà lẹ́yìn ibùdó.

14 Mose bínú sí àwọn olórí ogun náà ati sí olórí ẹgbẹẹgbẹrun ati olórí ọgọọgọrun-un.

15 Ó bi wọ́n pé, “Kí ló dé tí ẹ dá àwọn obinrin wọnyi sí?

16 Ṣé ẹ ranti pé àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu tí wọ́n sì mú àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ̀ sí OLUWA ní Peori, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ yìí ni àjàkálẹ̀ àrùn ṣe bẹ́ sílẹ̀ láàrin àwọn ọmọ Israẹli?

17 Nítorí náà ẹ pa gbogbo àwọn ọdọmọkunrin wọn, ati àwọn obinrin tí wọn ti mọ ọkunrin.

18 Ṣugbọn kí ẹ dá àwọn ọdọmọbinrin tí wọn kò tíì mọ ọkunrin sí, kí ẹ fi wọ́n ṣe aya fún ara yín.

19 Ǹjẹ́ nisinsinyii gbogbo àwọn tí ó bá ti paniyan tabi tí ó ti fọwọ́ kan òkú láàrin yín yóo dúró lẹ́yìn ibùdó fún ọjọ́ meje. Ní ọjọ́ kẹta ati ọjọ́ keje, àwọn ati obinrin tí wọ́n mú lójú ogun yóo ṣe ìwẹ̀nùmọ́.

20 Ẹ sì níláti fọ gbogbo aṣọ yín, ati gbogbo àwọn ohun èlò tí a fi awọ ṣe, tabi irun ewúrẹ́, tabi igi.”

21 Eleasari bá sọ fún wọn pé, “Ẹ gbọ́ ìlànà tí OLUWA ti fi lélẹ̀ láti ẹnu Mose.

22 Gbogbo wúrà, fadaka, idẹ, irin ati tánńganran ati òjé,

23 àní, gbogbo ohun tí kò bá ti lè jóná ni a óo mú la iná kọjá, kí á lè sọ wọ́n di mímọ́; a óo sì fi omi ìwẹ̀nùmọ́ fọ àwọn ohun èlò tí wọn bá lè jóná.

24 Ní ọjọ́ keje, ẹ níláti fọ aṣọ yín, kí ẹ sì di mímọ́, lẹ́yìn náà, ẹ óo pada wá sí ibùdó.”

Pípín Ìkógun

25 OLUWA sọ fún Mose pé,

26 “Ìwọ, Eleasari ati àwọn olórí, ẹ ka gbogbo ìkógun tí ẹ kó, ati eniyan ati ẹranko.

27 Pín gbogbo ìkógun náà sí meji, kí apákan jẹ́ ti àwọn tí wọ́n lọ sójú ogun, kí apá keji sì jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli yòókù.

28 Yọ apákan sílẹ̀ fún OLUWA lára ti àwọn tí wọ́n lọ sójú ogun, ninu ẹẹdẹgbẹta tí o bá kà ninu eniyan ati mààlúù ati kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ati ẹran ọ̀sìn, ọ̀kan jẹ́ ti OLUWA.

29 Yọ ọ́ lára ìkógun wọn kí o sì kó wọn fún Eleasari alufaa gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹbọ sí OLUWA.

30 Lára ìdajì tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, mú ẹyọ kan ninu araadọta ninu eniyan ati mààlúù ati kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ati ẹran ọ̀sìn; kí o sì kó wọn fún àwọn ọmọ Lefi tí ń ṣe ìtọ́jú ibi mímọ́ OLUWA.”

31 Mose ati Eleasari sì ṣe bí OLUWA ti pa á láṣẹ fún wọn.

32 Ìkógun tí ó kù ninu àwọn tí àwọn ọmọ ogun kó bọ̀ láti ojú ogun jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹrinlelọgbọn ó dín ẹgbẹẹdọgbọn (675,000) aguntan.

33 Ẹgbaa mẹrindinlogoji (72,000) mààlúù.

34 Ọ̀kẹ́ mẹta ó lé ẹgbẹrun (61,000) kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.

35 Àwọn ọdọmọbinrin tí kò tíì mọ ọkunrin jẹ́ ẹgbaa mẹrindinlogun (32,000).

36 Ìdajì rẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ ogun jẹ́ ẹgbaa mejidinlaadọsan-an ó lé ẹẹdẹgbẹjọ (337,500) aguntan.

37 Ìpín ti OLUWA ninu rẹ̀ jẹ́ ẹẹdẹgbẹrin ó dín mẹẹdọgbọn (675).

38 Mààlúù jẹ́ ẹgbaa mejidinlogun (36,000), ìpín ti OLUWA ninu rẹ̀ jẹ́ mejilelaadọrin.

39 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ jẹ́ ẹgbaa mẹẹdogun ó lé ẹẹdẹgbẹta (30,500), ìpín ti OLUWA ninu rẹ̀ jẹ́ mọkanlelọgọta.

40 Àwọn eniyan sì jẹ́ ẹgbaajọ (16,000), ìpín ti OLUWA jẹ́ mejilelọgbọn.

41 Mose kó ìpín ti OLUWA fún Eleasari alufaa gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti pàṣẹ fún un.

42 Ìdajì yòókù, tí ó jẹ́ ìpín àwọn ọmọ Israẹli tí kò lọ sójú ogun,

43 jẹ́ ẹgbaa mejidinlaadọsan-an ó lé ẹẹdẹgbẹjọ (337,500) aguntan.

44 Ẹgbaa mejidinlogun (36,000) mààlúù.

45 Ẹgbaa mẹẹdogun ó lé ẹẹdẹgbẹta (30,500) kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.

46 Àwọn eniyan sì jẹ́ ẹgbaa mẹjọ (16,000).

47 Ninu wọn, Mose mú ọ̀kọ̀ọ̀kan ninu araadọta ninu àwọn eniyan ati ẹranko, ó sì kó wọn fún àwọn ọmọ Lefi tí ń ṣe ìtọ́jú ibi mímọ́ OLUWA, bí OLUWA ti pàṣẹ fún un.

48 Lẹ́yìn náà ni àwọn olórí ogun àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹrun ati ọgọọgọrun-un tọ Mose wá, wọ́n wí pé,

49 “A ti ka àwọn ọmọ ogun tí ó wà lábẹ́ wa, kò sí ẹni tí ó kú sójú ogun.

50 Nítorí náà a mú ọrẹ ẹbọ: ohun ọ̀ṣọ́ wúrà, ẹ̀wọ̀n, ẹ̀gbà ọwọ́, òrùka, yẹtí, ati ìlẹ̀kẹ̀ wá fún OLUWA lára ìkógun wa, láti fi ṣe ẹbọ ètùtù fún wa níwájú OLUWA.”

51 Mose ati Eleasari gba àwọn ohun ọ̀ṣọ́ wúrà ati àwọn ohun ọ̀ṣọ́ mìíràn náà lọ́wọ́ wọn.

52 Ìwọ̀n gbogbo ọrẹ ẹbọ tí àwọn olórí ogun náà mú wá jẹ́ ẹgbaajọ ó lé ẹẹdẹgbẹrin ó lé aadọta (16,750) ṣekeli.

53 Àwọn ọmọ ogun tí wọn kì í ṣe olórí ogun ti kó ìkógun tiwọn.

54 Mose ati Eleasari kó wúrà náà lọ sinu Àgọ́ Àjọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli níwájú OLUWA.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24 25 26 27 28 29 30 31 32 33 34 35 36