3 Mose bá rán àwọn ọkunrin tí wọ́n jẹ́ olórí ninu ẹ̀yà wọn lọ, láti aṣálẹ̀ Parani.
4 Orúkọ wọn nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Reubẹni, ó rán Ṣamua ọmọ Sakuri;
5 láti inú ẹ̀yà Simeoni, ó rán Ṣafati ọmọ Hori;
6 láti inú ẹ̀yà Juda, ó rán Kalebu, ọmọ Jefune;
7 láti inú ẹ̀yà Isakari, ó rán Igali, ọmọ Josẹfu;
8 láti inú ẹ̀yà Efuraimu, ó rán Hoṣea ọmọ Nuni;
9 láti inú ẹ̀yà Bẹnjamini, ó rán Paliti, ọmọ Rafu;