15 “Ka iye àwọn ọmọkunrin Lefi gẹ́gẹ́ bí ìdílé baba wọn. Bẹ̀rẹ̀ láti ọmọ oṣù kan lọ sókè.”
16 Mose sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti pàṣẹ fún un.
17 Lefi ní ọmọkunrin mẹta: Geriṣoni, Kohati ati Merari, wọ́n sì jẹ́ olórí àwọn ìdílé wọn.
18 Orúkọ àwọn ọmọ Geriṣoni ni Libini ati Ṣimei.
19 Orúkọ àwọn ọmọ Kohati ni Amramu, Iṣari, Heburoni ati Usieli.
20 Orúkọ àwọn ọmọ Merari ni Mahili ati Muṣi. Àwọn ìdílé Lefi nìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
21 Geriṣoni ni baba ńlá àwọn ọmọ Libini ati àwọn ọmọ Ṣimei.