2 Nahaṣi ara Ammoni na si da wọn lohùn pe, Nipa bayi li emi o fi ba nyin da majẹmu, nipa yiyọ gbogbo oju ọtun nyin kuro, emi o si fi i ṣe ẹlẹyà li oju gbogbo Israeli.
3 Awọn agba Jabeṣi si wi fun u pe, Fun wa li ayè ni ijọ meje, awa o si ran onṣẹ si gbogbo agbegbe Israeli bi ko ba si ẹniti yio gbà wa, awa o si jade tọ ọ wá.
4 Awọn iranṣẹ na si wá si Gibea ti Saulu, nwọn rohìn na li eti awọn enia: gbogbo enia na si gbe ohùn wọn soke, nwọn si sọkun.
5 Si kiye si i, Saulu bọ̀ wá ile lẹhin ọwọ́ malu lati papa wá; Saulu si wipe, Ẽṣe awọn enia ti nwọn fi nsọkun? Nwọn si sọ ọ̀rọ awọn ọkunrin Jabeṣi fun u.
6 Ẹmi Ọlọrun si bà le Saulu nigbati o gbọ́ ọ̀rọ wọnni, inu rẹ̀ si ru pipọ.
7 O si mu malu meji, o rẹ́ wọn wẹwẹ, o si ran wọn si gbogbo agbegbe Israeli nipa ọwọ́ awọn onṣẹ na, wipe, Ẹnikẹni ti o wu ki o ṣe ti ko ba tọ Saulu ati Samueli lẹhin, bẹ̃ gẹgẹ li a o ṣe si malu rẹ̀. Ibẹ̀ru Oluwa si mu awọn enia na, nwọn si jade bi enia kanṣoṣo.
8 O si kà wọn ni Beseki, awọn ọmọ Israeli si jẹ ọkẹ mẹ̃dogun enia; awọn ọkunrin Juda si jẹ ẹgbã mẹ̃dogun.