1. Sam 25 YCE

Ikú Samuẹli

1 SAMUELI si kú; gbogbo enia Israeli si ko ara wọn jọ, nwọn sì sọkun rẹ̀, nwọn si sin i ninu ile rẹ̀ ni Rama. Dafidi si dide, o si sọkalẹ lọ si ijù Parani.

2 Ọkunrin kan si mbẹ ni Maoni, ẹniti iṣẹ rẹ̀ mbẹ ni Karmeli; ọkunrin na si pọ̀ gidigidi, o si ni ẹgbẹdogun agutan, ati ẹgbẹrun ewurẹ: o sì nrẹ irun agutan rẹ̀ ni Karmeli.

3 Orukọ ọkunrin na si njẹ Nabali, orukọ aya rẹ̀ si njẹ Abigaili; on si jẹ oloye obinrin, ati arẹwa enia; ṣugbọn onroro ati oniwa buburu ni ọkunrin; ẹni idile Kalebu li on si ṣe.

4 Dafidi si gbọ́ li aginju pe, Nabali nrẹ irun agutan rẹ̀.

5 Dafidi si ran ọmọkunrin mẹwa, Dafidi si sọ fun awọn ọdọmọkunrin na pe, Ẹ goke lọ si Karmeli, ki ẹ si tọ Nabali lọ, ki ẹ si ki i li orukọ mi.

6 Bayi li ẹ o si wi fun ẹniti o wà ni irọra pe, Alafia fun ọ, alafia fun ile rẹ, ati alafia fun ohun gbogbo ti iwọ ni.

7 Njẹ mo gbọ́ pe, awọn olùrẹrun mbẹ lọdọ rẹ; Wõ, awọn oluṣọ agutan rẹ ti wà lọdọ wa, awa kò ṣe wọn ni iwọsi kan, bẹ̃ni ohun kan ko si nù lọwọ wọn, ni gbogbo ọjọ ti nwọn wà ni Karmeli.

8 Bi awọn ọmọkunrin rẹ lere, nwọn o si sọ fun ọ. Nitorina jẹ ki awọn ọmọkunrin wọnyi ki o ri oju rere lọdọ rẹ; nitoripe awa sa wá li ọjọ rere: emi bẹ ọ, ohunkohun ti ọwọ́ rẹ ba bá, fi fun awọn iranṣẹ rẹ, ati fun Dafidi ọmọ rẹ.

9 Awọn ọmọkunrin Dafidi si lọ, nwọn si sọ fun Nabali gẹgẹ bi gbogbo ọ̀rọ wọnyi li orukọ Dafidi, nwọn si simi.

10 Nabali si da awọn iranṣẹ Dafidi lohùn, pe, Tani ijẹ Dafidi? tabi tani si njẹ ọmọ Jesse? ọ̀pọlọpọ iranṣẹ ni mbẹ nisisiyi ti nwọn sá olukuluku kuro lọdọ oluwa rẹ̀.

11 Njẹ ki emi ki o ha mu onjẹ mi, ati omi mi, ati ẹran mi ti mo pa fun awọn olùrẹrun mi, ki emi ki o si fi fun awọn ọkunrin ti emi kò mọ̀ ibi ti nwọn gbe ti wá?

12 Bẹ̃li awọn ọmọkunrin Dafidi si mu ọ̀na wọn pọ̀n, nwọn si pada, nwọn si wá, nwọn si rò fun u gẹgẹ bi gbogbo ọ̀rọ wọnyi.

13 Dafidi si wi fun awọn ọmọkunrin rẹ̀ pe, Ki olukuluku nyin ki o di idà rẹ̀ mọ idi. Olukuluku ọkunrin si di idà rẹ̀ mọ idi; ati Dafidi pẹlu si di idà tirẹ̀: iwọn irinwo ọmọkunrin si goke tọ Dafidi lẹhin; igba si joko nibi ẹrù.

14 Ọkan ninu awọn ọmọkunrin Nabali si wi fun Abigaili aya rẹ̀ pe, Wõ, Dafidi ran onṣẹ lati aginju wá lati ki oluwa wa; o si kanra mọ wọn.

15 Ṣugbọn awọn ọkunrin na ṣe ore fun wa gidigidi, nwọn kò ṣe wa ni iwọsi kan, ohunkohun kò nù li ọwọ́ wa, ni gbogbo ọjọ ti awa ba wọn rìn nigbati awa mbẹ li oko.

16 Odi ni nwọn sa jasi fun wa lọsan, ati loru, ni gbogbo ọjọ ti a fi ba wọn gbe, ti a mbojuto awọn agutan.

17 Njẹ si ro o wò, ki o si mọ̀ eyiti iwọ o ṣe; nitoripe ati gbero ibi si oluwa wa, ati si gbogbo ile rẹ̀: on si jasi ọmọ Beliali ti a ko le sọ̀rọ fun.

18 Abigaili si yara, o si mu igba iṣu akara ati igo ọti-waini meji, ati agutan marun, ti a ti sè, ati oṣuwọn agbado yiyan marun, ati ọgọrun idi ajara, ati igba akara eso ọpọtọ, o si di wọn ru kẹtẹkẹtẹ.

19 On si wi fun awọn ọmọkunrin rẹ̀ pe, Ma lọ niwaju mi; wõ, emi mbọ lẹhin nyin. Ṣugbọn on kò wi fun Nabali bale rẹ̀.

20 O si ṣe, bi o ti gun ori kẹtẹkẹtẹ, ti o si nsọkalẹ si ibi ikọkọ oke na, wõ, Dafidi ati awọn ọmọkunrin rẹ̀ si nsọ-kalẹ, niwaju rẹ̀; on si wá pade wọn.

21 Dafidi si ti wipe, Njẹ lasan li emi ti pa gbogbo eyi ti iṣe ti eleyi mọ li aginju, ti ohunkohun kò si nù ninu gbogbo eyi ti iṣe tirẹ̀; on li o si fi ibi san ire fun mi yi.

22 Bẹ̃ ati ju bẹ̃ lọ ni ki Ọlọrun ki o ṣe si awọn ọta Dafidi, bi emi ba fi ẹnikẹni ti ntọ̀ sara ogiri silẹ ninu gbogbo eyi ti iṣe tirẹ̀ titi di imọlẹ owurọ.

23 Abigaili si ri Dafidi, on si yara, o sọkalẹ lori kẹtẹkẹtẹ, o si dojubolẹ niwaju Dafidi, o si tẹ ara rẹ̀ ba silẹ.

24 O si wolẹ li ẹba ẹsẹ rẹ̀ o wipe, Oluwa mi, fi ẹ̀ṣẹ yi ya mi: ki o si jẹ ki iranṣẹbinrin rẹ, emi bẹ̀ ọ, sọ̀rọ leti rẹ, ki o si gbọ́ ọ̀rọ iranṣẹbinrin rẹ.

25 Oluwa mi, emi bẹ̀ ọ, má ka ọkunrin Beliali yi si, ani Nabali: nitoripe bi orukọ rẹ̀ ti jẹ bẹ̃li on na ri: Nabali li orukọ rẹ̀, aimoye si wà pẹlu rẹ̀; ṣugbọn emi iranṣẹbinrin rẹ kò ri awọn ọmọkunrin oluwa mi, ti iwọ rán.

26 Njẹ, oluwa mi, bi Oluwa ti wà lãye, ati bi ẹmi rẹ si ti wà làye, bi Oluwa si ti da ọ duro lati wá ta ẹjẹ silẹ, ati lati fi ọwọ́ ara rẹ gbẹsan; njẹ, ki awọn ọta rẹ, ati awọn ẹniti ngbero ibi si oluwa mi ri bi Nabali.

27 Njẹ eyi ni ẹbùn ti iranṣẹbinrin rẹ mu wá fun oluwa mi, jẹ ki a si fi fun awọn ọmọkunrin ti ntọ oluwa mi lẹhin.

28 Emi bẹ̀ ọ, fi irekọja iranṣẹbinrin rẹ ji i: nitori ti Oluwa yio sa ṣe ile ododo fun oluwa mi, nitori ogun Oluwa ni oluwa mi njà; a kò si ri ibi lọwọ rẹ ni gbogbo ọjọ rẹ.

29 Ọkunrin kan si dide lati ma lepa rẹ, ati lati ma wá ẹmi rẹ: ṣugbọn a o si di ẹmi oluwa mi ninu idi ìye lọdọ Oluwa Ọlọrun rẹ; ati ẹmi awọn ọta rẹ li a o si gbọ̀n sọnù gẹgẹ bi kànakana jade.

30 Yio si ṣe, Oluwa yio ṣe si oluwa mi gẹgẹ bi gbogbo ire ti o ti wi nipa tirẹ, yio si yan ọ li alaṣẹ lori Israeli.

31 Eyi ki yio si jasi ibinujẹ fun ọ, tabi ibinujẹ ọkàn fun oluwa mi, nitoripe iwọ ta ẹjẹ alaiṣẹ silẹ, tabi pe oluwa mi gbẹsan fun ara rẹ̀: ṣugbọn nigbati Oluwa ba ṣe ore fun oluwa mi, njẹ ranti iranṣẹbinrin rẹ.

32 Dafidi si wi fun Abigaili pe, Alabukun fun Oluwa Ọlọrun Israeli, ti o ran ọ loni yi lati pade mi.

33 Ibukun ni fun ọgbọn rẹ, alabukunfun si ni iwọ, ti o da mi duro loni yi lati wá ta ẹjẹ silẹ, ati lati fi ọwọ́ mi gbẹsan fun ara mi.

34 Nitõtọ bi Oluwa Ọlọrun Israeli ti mbẹ, ti o da mi duro lati pa ọ lara, bikoṣepe bi iwọ ti yara ti o si ti wá pade mi, nitotọ ki ba ti kù fun Nabali di imọlẹ owurọ ninu awọn ti o ntọ̀ sara ogiri.

35 Bẹ̃ni Dafidi si gbà nkan ti o mu wá fun u li ọwọ́ rẹ̀, o si wi fun u pe, Goke lọ li alafia si ile rẹ, wõ, emi ti gbọ́ ohun rẹ, inu mi si dùn si ọ.

36 Abigaili si tọ̀ Nabali wá, si wõ, on si se asè ni ile rẹ̀ gẹgẹ bi ase ọba; inu Nabali si dùn nitoripe, o ti mu ọti li amupara; on kò si sọ nkan fun u, diẹ tabi pupọ: titi di imọlẹ owurọ.

37 O si ṣe; li owurọ, nigbati ọti na si dá tan li oju Nabali, obinrin rẹ̀ si rò nkan wọnni fun u, ọkàn rẹ̀ si kú ninu, on si dabi okuta.

38 O si ṣe lẹhin iwọn ijọ mẹwa, Oluwa lù Nabali, o si kú.

39 Dafidi si gbọ́ pe Nabali kú, o si wi pe, Iyin ni fun Oluwa ti o gbeja gigàn mi lati ọwọ́ Nabali wá, ti o si da iranṣẹ rẹ̀ duro lati ṣe ibi: Oluwa si yi ikà Nabali si ori on tikalarẹ̀. Dafidi si ranṣẹ, o si ba Abigaili sọ̀rọ lati mu u fi ṣe aya fun ara rẹ̀.

40 Awọn iranṣẹ Dafidi si lọ sọdọ Abigaili ni Karmeli, nwọn si sọ fun u pe, Dafidi rán wa wá si ọ lati mu ọ ṣe aya rẹ̀.

41 O si dide, o si dojubolẹ, o si wipe, Wõ, jẹ ki iranṣẹbinrin rẹ ki o jẹ iranṣẹ kan lati ma wẹ ẹsẹ awọn iranṣẹ oluwa mi.

42 Abigaili si yara, o dide, o si gun kẹtẹkẹtẹ, awọn iranṣẹbinrin rẹ̀ marun si tẹle e lẹhin; on si tẹle awọn iranṣẹ Dafidi, o si wa di aya rẹ̀.

43 Dafidi si mu Ahinoamu ti Jesreeli; awọn mejeji si jẹ aya rẹ̀.

44 Ṣugbọn Saulu ti fi Mikali ọmọ rẹ̀ obinrin, aya Dafidi, fun Falti ọmọ Laisi ti iṣe ara Gallimu.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24 25 26 27 28 29 30 31