31 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Pékà, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Ísírẹ́lì?
32 Ní ọdún keje Pékà ọmọ Remalíà ọba Ísírẹ́lì, Jótamù ọmọ Ùsáyà ọba Júdà bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba.
33 Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba. Ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún mẹ́rìndínlógún. Orúkọ ìyá a rẹ̀ a máa jẹ́ Jérúṣà ọmọbìnrin Ṣádókù.
34 Ó ṣe ohun tí ó tọ́ lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí bàbá a rẹ̀ Ùsáyà ti ṣe.
35 Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò sí wọn kúrò; Àwọn ènìyàn tẹ̀ṣíwájú láti rú ẹbọ àti láti sun tùràrí níbẹ̀: Jótamù tún ìlẹ̀kùn gíga tó ń kọ́ ní ti ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.
36 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Jótamù, àti ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Júdà?
37 (Ní ayé ìgbà a nì, Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní rán Résínì ọba Ṣíríà àti Pékà ọmọ Remálíà láti dojúkọ Júdà).