Deutarónómì 2:8-14 BMY

8 Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Ísọ̀ tí ń gbé ní Séírì. A yà kúrò ní ọ̀nà aginjù èyí tí ó wá láti Élátì àti Ésíóni-Gébérì, a sì rìn gba ọ̀nà ihà Móábù.

9 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Móábù bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Árì fún àwọn ọmọ Lọ́tì bí i ìní.”

10 Àwọn Émímù ti gbé ibẹ̀ rí: Àwọn ènìyàn tó sígbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Ánákì.

11 Gẹ́gẹ́ bí Ánákì àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Ráfátì ṣùgbọ́n àwọn ará Móábù pè wọ́n ní Émímù.

12 Àwọn ará Hórì gbé ní Séírì kí àwọn ọmọ Ísọ̀ tó lé wọn kúrò níwájú wọn, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, (wọ́n tẹ̀dó sí àyè wọn) gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.

13 Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Sérádì kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.

14 Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì (38) kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Sérédì kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadesi Báníyà. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrin àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrin àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.