4 Àwọn orílẹ̀ èdè gbọ́ nípa rẹ̀,wọ́n sì fi ẹ̀wọ̀n mú un nínú ààfin wọn.Wọn fi ẹ̀wọ̀n mu nu lọ sí ilẹ̀ Éjíbítì.
5 “ ‘Nígbà tí abo kìnìún yìí rí pé ìrètí rẹ̀ sì já sí asán,ó mú ọmọ rẹ̀ mìíràn ó sì tún tọ́ ọ dàgbà di kìnnìún tó ní agbára.
6 Ó sì ń rìn káàkiri láàrin àwọn kìnnìún nítorí pé ó ti lágbára,o kọ ọdẹ ṣíṣe, ó sì pa àwọn ènìyàn.
7 Ó sì wó odi wọn palẹ̀ ó sì sọ àwọ̀n ìlú wọn di ahoro.Ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé ibẹ̀ sì wà ní ìpayà nítorí bíbú ramúramù rẹ̀.
8 Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀ èdè tó yìí ká dìde sí i,wọn ta ẹ̀wọ̀n fún un, wọn sì mú nínú ihò wọn.
9 Wọn fi ìkọ́ gbé e sínú ago, wọn mú un lọ sí ọ̀dọ̀ Ọba Bábílónì,wọn fi sínú ìhámọ́, a kò sì gbọ́ bíbú rẹ̀ mọ́ lórí òkè Ísírẹ́lì.
10 “ ‘Ìyá rẹ dàbí àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ̀;tí á gbìn sí etí odò ó, kún fún èso,ó sì kún fún ẹ̀ka nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi,