2 “Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
3 Wọn ń ṣe panṣágà ní Éjíbítì, wọn ń ṣe panṣaga láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
4 Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Óhólà, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Óhólíbà. Tèmí ni wọn, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Óhólà ni Samaríà, Óhólíbà sì ni Jérúsálẹ́mù.
5 “Óhólà ń ṣe asẹ́wó nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ́ sí àwọn olólùfẹ̀ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Ásíríà.
6 Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹsin.
7 O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Ásíríà gẹ́gẹ́ bí pansága obìnrin, o fi òrìsà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
8 kò fi ìwa aṣẹ́wó tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Éjíbítì sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúùfẹ́ sí i.