33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí Ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn.
34 Ìkúùkù Olúwa wà lórí wọn lọ́sán nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.
35 Nígbàkigbà tí àpótí Ẹ̀rí bá gbéra Mósè yóò sì wí pé;“Dìdé, Olúwa!Kí a tú àwọn ọ̀ta rẹ ká,kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”
36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé;“Padà, Olúwa,Sọ́dọ̀ àwọn àìmọye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Ísírẹ́lì.”