Nọ́ḿbà 22:30-36 BMY

30 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sọ fún Bálámù pé, “Ṣé mi kì í ṣe kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ ni, tí o máa ń gùn ní gbogbo ìgbà, láti ìgbà pípẹ́ wá? Ǹjẹ́ mo hu irú ìwà báyìí sí ọ rí?”“Rárá,” Ó dáhùn.

31 Nígbà náà Olúwa sí ojú Bálámù, ó sì rí ángẹ́lì Olúwa tí ó dúró ní oju ọ̀nà pẹ̀lú idà rẹ̀ tí ó fàyọ. Ó sì tẹ orí rẹ̀ ba.

32 Nígbà náà ángẹ́lì Olúwa bèèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí o fi na kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ nígbà mẹ́ta yìí? Mo wá síbí láti kọ ojú ìjà sí ọ nítorí ọ̀nà rẹ kò tọ́ níwájú mi.

33 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí mi ó sì yà kúrò fún mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta yìí. Tí ó bá jẹ́ wí pé kò yà kúrò. Èmi kì ìbá ti pa ọ́ pátapáta nísinsìnyìí, ṣùgbọ́n Èmi yóò sì dá òun sí.”

34 Bálámù sọ fún ángẹ́lì Olúwa pé, “Mo ti dẹ́ṣẹ̀, èmi kò mọ̀ pé o dúró níwájú ọ̀nà láti dojú kọ mí, Nísinsin yìí tí inú rẹ kò bá dùn, èmi ó padà.”

35 Ańgẹ́lì Olúwa sọ fún Bálámù pé, “Lọ pẹ̀lú àwọn arákùnrin náà, ṣùgbọ́n nǹkan tí mo sọ fún ọ nìkan ni kí o sọ.” Nígbà náà Bálámù lọ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Bálákì.

36 Nígbà tí Bálákì gbọ́ pé Bálámù ń bọ̀ wá, ó jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀ ní ìlú Móábù tí ó wà ní agbégbé Ánónì, ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ̀.