Ìṣe Àwọn Àpósítélì 18:21-27 BMY

21 Ṣùgbọ́n ó dágbére fún wọn, ó sì wí pé, (Èmi kò gbọdọ̀ má ṣe àjọ ọdún tí ń bọ̀ yìí ni Jerúsálémù bí ó tí wù kí ó rí: ṣùgbọ́n) “Èmi ó tún padà tọ̀ yín wá, bí Ọlọ́run bá fẹ́.” Ó sì ṣíkọ̀ láti Éfésù.

22 Nígbà tí ó sì tí gúnlẹ̀ ni Keṣaríà; tí ó gòkè, tí ó sì kí ijọ, ó sọ̀kalẹ̀ lọ sì Áńtíókù.

23 Nígbà tí ó sì gbé ọjọ́ díẹ̀ níbẹ, ó lọ, ó sì kọjá lọ láti Gálátíà àti Fírígíà, ó mú gbogbo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn lọ́kàn le.

24 Júù kan sì wà tí a ń pè ni Àpólò, tí a bí ni Alekisáńdíríà, ó wá sí Éféṣù. Ó nì ẹ̀bùn ọ̀rọ̀-sísọ, ó sì mọ ìwé mímọ́ púpọ̀;

25 Ọkùnrin yìí ni a tí kọ́ ní ọ̀nà tí Olúwa; ó sì ṣe ẹni tí ó ní ìtara tí ẹ̀mí, ó ń sọ̀rọ̀ ó sì ń kọ́ni ní àwọn ohun tí i ṣe ti Olúwa dáradára; kìkì bamitíìsímù tí Jòhánù ní ó mọ̀.

26 Ó sì bẹ̀rẹ̀ ṣí fi ìgboyà sọ̀rọ̀ ni Sínágọ́gù: nígbà tí Àkúílà àti Pìrìskílà gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, wọ́n mú un sọ́dọ̀ wọ́n sì túbọ̀ sọ ọ̀nà Ọlọ́run fún un dájúdájú.

27 Nígbà tí ó sì ń fẹ́ kọjá lọ sì Ákáyà, àwọn arakùnrin gbà á ní ìyànjú, wọ́n sì kọ̀wé sí àwọn ọmọ-ẹ̀hìn kí wọ́n gbà á: nígbà tí ó sì dé, ó ràn àwọn tí ó gbàgbọ́ nípasẹ̀ oore-ọfẹ lọ́wọ́ púpọ̀,