1 Ọ̀kan nínú àwọn ańgẹ́lì méje náà tí ó ní ìgò méje wọ̀n-ọn-nì sì wá, ó sì ba mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wá níhìn-ín; èmi ó sì fi ìdájọ́ àgbèrè ńlá ní tí ó jókòó lórí omi púpọ̀ han ọ:
2 Ẹni tí àwọn ọba ayé bá ṣe àgbèrè, tí a sì fi ọtí wáìnì àgbèrè rẹ̀ pá àwọn tí ń gbé inú ayé.”
3 Ó sì gbé mi nínú ẹ̀mí lọ sí ihà: mo sì rí obìnrin kan ó jòkòó lórí ẹranko aláwọ̀ òdòdó kan tí ó kún fún orúkọ ọ̀rọ̀ òdì, ó ní orí méje àti ìwo mẹ́wàá.
4 A sì fi aṣọ elése àlùkò àti aṣọ odòdó wọ obìnrin náà, a sì fi wúrà àti òkúta iyebíye àti pérílì ṣe é lọ́sọ̀ọ́, ó ní ago wúrà kan ní ọwọ́ rẹ̀, tí ó kún fún ìríra àti fún ẹ̀gbin àgbérè rẹ̀;
5 Àti níwájú rẹ̀ ni orúkọ kan tí a kọ:OHUN ÌJÌNLẸ̀BÁBÍLÓNÌ ŃLÁÌYÁ ÀWỌN PANṢÁGÀÀTI ÀWỌN OHUN ÌRÍRA AYÉ.
6 Mo sì rí obìnrin náà mu ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́, àti ẹ̀jẹ̀ àwọn ajẹ́rìí ikú Jésù ní àmuyó.Nígbà tí mo sì rí i, ẹnu yà mi gidigidi.
7 Ańgẹ́lì sì wí fún mi pé, “Nítorí kí ni ẹnu ṣe yà ọ́? Èmi ó sọ ti ìjìnlẹ̀ obìnrin náà fún ọ, àti ti ẹranko tí ó gùn, ti ó ní orí méje àti ìwo mẹ́wàá.