Ìfihàn 18:4-10 BMY

4 Mo sì gbọ́ ohùn mìíràn láti ọ̀run wá, wí pé:“Ẹ ti inú rẹ̀ jáde, ẹ̀yin ènìyàn mi,kí ẹ ma bàá ṣe alábàápín nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,kí ẹ ma bàá si ṣe gbà nínú ìyọnu rẹ̀.

5 Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ ga títí dé ọ̀run,Ọlọ́run sì ti rántí àìsedédé rẹ̀.

6 San an fún un, àní bí òun tí san án fún ní,kí ó sì ṣe e ni ìlọ́po méjì fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀Nínú ago náà tí o ti kún, òun ni kí ẹ sì kún fún un ni méjì.

7 Níwọ̀n bí o ti yin ara rẹ̀ lógo tó,tí ó sì hùwà wọ̀bìà,níwọ̀n bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ dá a lóró kí ẹ sì fún un ní ìbànújẹ́;nítorí tí ó wí ní ọkàn rẹ̀ pé,‘Mo jókòó bí ọbabìnrin,èmi kì sì í ṣe opó, èmí kì yóò sì rí ìbànújẹ́ láé.’

8 Nítorí náà, ní ìjọ kan ni ìyọnu rẹ̀ yóò dé,ìkú, àti ìbìnújẹ́, àti ìyàn;a ó sì fi iná sun ún pátapáta:nítorí pé alágbára ni Olúwa Ọlọ́run tí ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.

9 “Àti àwọn ọba ayé, tí ó ti ń bá a ṣe àgbérè, ti wọn sì ń hùwà wọ̀bìà, yóò sì pohùnréré ẹkún lé e lórí, nígbà tí wọn bá wo èéfín ìjóná rẹ̀.

10 Wọ́n ó dúró ní òkèrè réré nítorí ìbẹ̀rù iṣẹ́ oró rẹ̀, wọn ó máa wí pé:“ ‘Ègbé! Ègbé, ni fún ìlú ńlá náà,Bábílónì ìlú alágbára nì!Nítorí ní wákàtí kan ni ìdájọ́ rẹ dé!’