11 Bí ẹyẹ idì tií tú ìtẹ́ rẹ̀ ká,láti kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ bí à á tíí fò,tíí sì í na apá rẹ̀ láti hán wọntí wọ́n bá fẹ́ já bọ́,bẹ́ẹ̀ ni OLUWA ń ṣe sí Israẹli.
12 OLUWA nìkan ṣoṣo ni ó ṣáájú àwọn eniyan rẹ̀,láìsí ìrànlọ́wọ́ oriṣa kankan.
13 “Ó fi wọ́n jọba lórí àwọn òkè ayé,ó sì fún wọn ní èso ilẹ̀ jẹ.Ó pèsè oyin fún wọn láti inú àpáta,ó sì mú kí igi olifi hù fún wọn lórí ilẹ̀ olókùúta.
14 Wọn rí ọpọlọpọ wàrà lára mààlúù wọn,ati ọ̀pọ̀ omi wàrà lára ewúrẹ́ wọn,ó fún wọn ní ọ̀rá ọ̀dọ́ aguntan ati ti àgbò,ó fún wọn ní mààlúù Baṣani, ati ewúrẹ́,ati ọkà tí ó dára jùlọ,ati ọpọlọpọ ọtí waini.
15 “Ṣugbọn ẹ̀yin ọmọ Jeṣuruni, ẹ yó tán,ẹ wá tàpá sí àṣẹ;ẹ rí jẹ, ẹ rí mu, ẹ sì lókun lára;ẹ wá gbàgbé Ọlọrun tí ó da yín,ẹ sì ń pẹ̀gàn àpáta ìgbàlà yín!
16 Wọ́n fi ìbọ̀rìṣà wọn sọ OLUWA di òjòwú;wọ́n fi ìwà burúkú wọn mú kí ibinu OLUWA wọn ru sókè.
17 Wọ́n tún bẹ̀rẹ̀ sí rúbọ sí àwọn ẹ̀mí burúkú,Àwọn oriṣa tí wọn kò mọ̀ rí,tí àwọn baba wọn kò sì bọ rí.