Joṣua 15 BM

Ilẹ̀ Tí Wọ́n Pín fún Ẹ̀yà Juda

1 Àpèjúwe ìpín tí ó kan ẹ̀yà Juda lára ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli gbà, tí a pín fún wọn gẹ́gẹ́ bí iye ìdílé wọn nìyí:Ilẹ̀ náà lọ títí dé apá ìhà gúsù, ní ààlà ilẹ̀ Edomu, títí dé aṣálẹ̀ Sini.

2 Ààlà ilẹ̀ wọn, ní ìhà gúsù lọ láti òpin Òkun Iyọ̀,

3 láti apá etí òkun tí ó kọjú sí ìhà gúsù lọ títí dé àtigun òkè Akirabimu. Ó lọ títí dé Sini, ó tún lọ sí apá gúsù Kadeṣi Banea. Ó kọjá lọ lẹ́bàá Hesironi títí dé Adari, kí ó tó wá yípo lọ sí ìhà Kaka.

4 Lẹ́yìn náà, ó lọ títí dé Asimoni, ó tọ ipa odò Ijipti, ó sì pin sí Òkun Mẹditarenia. Òun ni yóo jẹ́ ààlà ilẹ̀ Juda ní apá ìhà gúsù.

5 Òkun Iyọ̀ ni ààlà ilẹ̀ náà ní apá ìlà oòrùn, ó lọ títí dé ibi tí odò Jọdani ti ń ṣàn wọ inú òkun.Níbẹ̀ ni ààlà rẹ̀ ní apá àríwá ti bẹ̀rẹ̀,

6 ó lọ títí dé Beti Hogila, ó lọ dé ìhà àríwá Betaraba, ó tún lọ títí dé ibi òkúta Bohani ọmọ Reubẹni.

7 Ó lọ láti àfonífojì Akori títí dé Debiri, ó wá yípo lọ sí apá ìhà àríwá, lọ sí Giligali, tí ó dojú kọ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Adumimu, tí ó wà ní apá gúsù àfonífojì náà. Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ibi odò Enṣemeṣi, ó sì pin sí Enrogeli.

8 Ààlà náà tún lọ sí apá òkè, sí àfonífojì ọmọ Hinomu ní apá gúsù òkè àwọn ará Jebusi (tíí ṣe ìlú Jerusalẹmu). Ó tún lọ títí dé orí òkè náà, tí ó dojú kọ àfonífojì ọmọ Hinomu, ní apá ìwọ̀ oòrùn, ní òpin ìhà àríwá àfonífojì Refaimu.

9 Láti ibẹ̀, ó tún bẹ̀rẹ̀ láti orí òkè títí dé odò Nefitoa, ó lọ sí apá ibi tí àwọn ìlú ńláńlá wà lẹ́bàá òkè Efuroni, ó wá pada sí apá Baala (tí a tún ń pè ní Kiriati Jearimu.)

10 Ààlà náà tún yípo lọ sí ìwọ̀ oòrùn Baala, sí apá òkè Seiri, lọ sí apá ìhà àríwá òkè Jearimu (tí a tún ń pè ní Kesaloni), ó bá tún dà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ lọ sí Beti Ṣemeṣi títí dé ìkọjá Timna.

11 Ó tún gba ti àwọn òkè tí ó wà ní ìhà àríwá Ekironi, ó wá yípo lọ sí Ṣikeroni. Lẹ́yìn náà, ó kọjá lọ sí òkè Baala títí dé Jabineeli, ó wá lọ parí sí Òkun Mẹditarenia.

12 Òkun yìí ni ààlà ilẹ̀ náà ní apá ìwọ̀ oòrùn.Òun ni ààlà ilẹ̀ àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bí iye ìdílé wọn.

Kalebu Ṣẹgun Heburoni ati Debiri

13 Gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti pàṣẹ fún Joṣua, ó fún Kalebu ọmọ Jefune ní Heburoni gẹ́gẹ́ bí ìpín tirẹ̀ ninu ilẹ̀ ẹ̀yà Juda. Orúkọ Heburoni tẹ́lẹ̀ ni Kiriati Ariba, (tí a tún ń pè ní ìlú Ariba), Ariba yìí ni baba Anaki.

14 Kalebu lé àwọn ìran Anaki mẹtẹẹta jáde níbẹ̀, àwọn ni ìran Ṣeṣai, ìran Ahimani, ati ìran Talimai.

15 Láti ibẹ̀ ó lọ gbógun ti àwọn ará ìlú Debiri. Orúkọ Debiri tẹ́lẹ̀ ni Kiriati Seferi.

16 Kalebu ṣe ìlérí pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣẹgun Kiriati Seferi tí ó sì gba ìlú náà ni òun yóo fún ní Akisa ọmọ òun, láti fi ṣe aya.

17 Otinieli ọmọ Kenasi, arakunrin Kalebu, ni ó ṣẹgun ìlú náà. Kalebu bá fi Akisa ọmọ rẹ̀ fún un láti fi ṣe aya.

18 Nígbà tí Akisa dé ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ̀, ó rọ ọkọ rẹ̀ pé kí ó tọrọ ilẹ̀ kan lọ́wọ́ baba òun. Ní ọjọ́ kan, bí Akisa ti sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, baba rẹ̀ bi í pé, “Kí ni ò ń fẹ́?”

19 Akisa dá baba rẹ̀ lóhùn pé, “Fún mi ní ẹ̀bùn, níwọ̀n ìgbà tí o ti fún mi ní ilẹ̀ Nẹgẹbu, fún mi ní àwọn orísun omi pẹlu.” Kalebu bá fún un ní àwọn orísun omi tí wọ́n wà lókè ati àwọn tí wọ́n wà ní ìsàlẹ̀.

Àwọn Ìlú Ńláńlá Tí Wọ́n Wà ní Juda

20 Èyí ni ilẹ̀ ẹ̀yà Juda gẹ́gẹ́ bí iye ìdílé wọn,

21 àwọn ìlú tí ó jẹ́ tiwọn ní ìpẹ̀kun apá ìhà gúsù lẹ́bàá ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabiseeli, Ederi, Jaguri,

22 Kina, Dimona, Adada,

23 Kedeṣi, Hasori, Itinani;

24 Sifi, Telemu, Bealoti;

25 Hasori Hadata, Kerioti Hesironi (tí a tún ń pè ní Hasori);

26 Amamu, Ṣema, Molada;

27 Hasari Gada, Heṣimoni, Betipeleti;

28 Hasari Ṣuali, Beeriṣeba, Bisiotaya;

29 Baala, Iimu, Esemu;

30 Elitoladi, Kesili, Horima;

31 Sikilagi, Madimana, Sansana;

32 Lebaotu, Ṣilihimu, Aini ati Rimoni; gbogbo ìlú ati ìletò wọn jẹ́ mọkandinlọgbọn.

33 Àwọn ìlú wọn tí wọ́n wà ní ẹsẹ̀ òkè nìwọ̀nyí: Eṣitaolu, Sora, Aṣinai.

34 Sanoa, Enganimu, Tapua, Enamu;

35 Jarimutu, Adulamu, Soko, Aseka;

36 Ṣaaraimu, Aditaimu, Gedera, Gederotaimu; gbogbo ìlú ati ìletò wọn jẹ́ mẹrinla.

37 Senani, Hadaṣa, Migidaligadi,

38 Dileani, Misipa, Jokiteeli,

39 Lakiṣi, Bosikati, Egiloni, Kaboni;

40 Lahimami, Kitiliṣi; Gederotu;

41 Beti Dagoni, Naama, ati Makeda; gbogbo ìlú ati ìletò wọ́n jẹ́ mẹrindinlogun.

42 Libina, Eteri, Aṣani, Ifita;

43 Aṣinai, Nesibu, Keila;

44 Akisibu, ati Mareṣa; gbogbo ìlú ati ìletò wọ́n jẹ́ mẹsan-an.

45 Ekironi pẹlu àwọn ìlú ati ìletò rẹ̀;

46 láti Ekironi títí dé etí òkun Mẹditarenia, ati gbogbo àwọn ìlú tí wọ́n wà lẹ́bàá Aṣidodu pẹlu àwọn ìletò wọn.

47 Aṣidodu, pẹlu àwọn ìlú ati àwọn ìletò rẹ̀; Gasa, pẹlu àwọn ìlú ati àwọn ìletò rẹ̀ títí dé odò Ijipti, ati etí òkun Mẹditarenia, pẹlu agbègbè rẹ̀.

48 Àwọn ìlú tí wọ́n wà ní orí òkè nìwọ̀nyí: Ṣamiri,

49 Jatiri, Soko, Dana, Kiriati Seferi (tí à ń pè ní Debiri),

50 Anabu, Eṣitemoa, Animi,

51 Goṣeni, Holoni, ati Gilo; gbogbo ìlú ati ìletò wọn jẹ́ mọkanla.

52 Arabu, Duma, Eṣani, Janimu,

53 Beti Tapua, Afeka, Humita,

54 Kiriati Ariba (tí à ń pè ní Heburoni), ati Siori, gbogbo ìlú ati ìletò wọn jẹ́ mẹsan-an.

55 Maoni, Kamẹli, Sifi, Juta.

56 Jesireeli, Jokideamu, Sanoa,

57 Kaini, Gibea, ati Timna, gbogbo ìlú ati ìletò wọn jẹ́ mẹ́wàá.

58 Halihuli, Betisuri, Gedori,

59 Maarati, Betanotu, ati Elitekoni, gbogbo ìlú ati ìletò wọn jẹ́ mẹfa.

60 Kiriati Baali (tí wọn ń pè ní Kiriati Jearimu), ati Raba, gbogbo ìlú ati ìletò wọn jẹ́ meji.

61 Àwọn ìlú tí wọ́n wà ní aṣálẹ̀ ni, Betaraba, Midini, Sekaka;

62 Nibiṣani, Ìlú Iyọ̀, ati Engedi; gbogbo ìlú ati ìletò wọn jẹ́ mẹfa.

63 Ṣugbọn àwọn eniyan Juda kò lè lé àwọn Jebusi tí wọn ń gbé inú ilẹ̀ Jerusalẹmu jáde. Àwọn Jebusi yìí sì tún wà láàrin àwọn eniyan Juda ní Jerusalẹmu títí di òní olónìí.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24