21 Lẹ́yìn wọn ni àwọn ọmọ Kohati tí wọ́n ru àwọn ohun èlò mímọ́ tó ṣí. Èyí jẹ́ kí àwọn ọmọ Geriṣoni ati àwọn ọmọ Merari rí ààyè láti pa Àgọ́ Àjọ náà kí àwọn ọmọ Kohati tó dé.
22 Lẹ́yìn náà ni àwọn tí wọ́n wà lábẹ́ ọ̀págun ẹ̀yà Efuraimu ṣí, wọ́n tò ní ìsọ̀rí-ìsọ̀rí. Eliṣama ọmọ Amihudu ni olórí wọn.
23 Gamalieli ọmọ Pedasuri ni olórí ẹ̀yà Manase.
24 Olórí ẹ̀yà Bẹnjamini sì ni Abidani ọmọ Gideoni.
25 Ní ìparí, àwọn ẹ̀yà tí wọ́n wà lábẹ́ ọ̀págun Dani ṣí, wọ́n tò ní ìsọ̀rí-ìsọ̀rí. Ahieseri ọmọ Amiṣadai ni olórí wọn.
26 Pagieli ọmọ Okirani ni olórí ẹ̀yà Aṣeri.
27 Olórí ẹ̀yà Nafutali sì ni Ahira ọmọ Enani.