16 OLUWA rán Balaamu pada sí Balaki pẹlu ohun tí yóo sọ.
17 Nígbà tí ó pada dé ó bá Balaki ati àwọn àgbààgbà Moabu, wọ́n dúró ti ẹbọ sísun náà, Balaki sì bèèrè ohun tí OLUWA sọ lọ́wọ́ rẹ̀.
18 Balaamu bá bẹ̀rẹ̀ sí fi òwe sọ̀rọ̀, ó ní:“Balaki, dìde, wá gbọ́,fetí sí mi, ọmọ Sipori;
19 Ọlọrun kò jọ eniyan tí máa ń purọ́,bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe eniyan tí máa ń yí ọkàn pada.Ohun tí ó bá ti sọ ni yóo ṣe,bí ó bá sì sọ̀rọ̀ yóo rí bẹ́ẹ̀.
20 OLUWA ti sọ fún mi pé kí n bukun wọn,Ọlọrun pàápàá ti bukun wọn, èmi kò lè mú ibukun náà kúrò.
21 Kò rí ìparun ninu Jakọbu,bẹ́ẹ̀ ni kò rí ìpọ́njú níwájú Israẹli.OLUWA Ọlọrun wọn wà pẹlu wọn,Òun sì ni ọba wọn.
22 OLUWA mú wọn jáde láti Ijipti wá,Ó sì ń jà fún wọn bí àgbáǹréré.