6 nítorí náà OLUWA wí pé àwọn ọmọbinrin Selofehadi ní ẹ̀tọ́ láti fẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wù wọ́n, ṣugbọn ó gbọdọ̀ jẹ́ láti inú ẹ̀yà wọn.
7 Ilẹ̀-ìní ẹ̀yà kan kò gbọdọ̀ di ti ẹ̀yà mìíràn, ilẹ̀ ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ wà ní ìkáwọ́ rẹ̀.
8 Obinrin tí ó bá ní ilẹ̀-ìní gbọdọ̀ fẹ́ ọkọ láàrin ẹ̀yà rẹ̀, kí olukuluku àwọn ọmọ Israẹli lè máa jogún ilẹ̀ ìní baba rẹ̀.”
9 Ilẹ̀-ìní ẹ̀yà kan kò gbọdọ̀ di ti ẹ̀yà mìíràn, ilẹ̀ ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ wà ní ìkáwọ́ rẹ̀.
10 Àwọn ọmọbinrin Selofehadi ṣe gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí OLUWA fún Mose;
11 Mahila, Tirisa, Hogila, Milika ati Noa fẹ́ ọkọ láàrin àwọn arakunrin baba wọn, gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti pa á láṣẹ.
12 Wọ́n fẹ́ ọkọ láàrin ẹ̀yà Manase ọmọ Josẹfu, ilẹ̀-ìní wọn sì dúró ninu ẹ̀yà baba wọn.