19 Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkèàti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo,wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ òkun,nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”
20 Ní ti Gádì ó wí pé:“Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gádì gbilẹ̀!Gádì ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún,ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
21 Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀;ìpín olórí ni a sì fi fún un.Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ,ó mú òdodo Olúwa se,àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.”
22 Ní ti Dánì ó wí pé:“Ọmọ kìnnìún ni Dánì,tí ń fò láti Básánì wá.”
23 Ní ti Náfítánì ó wí pé,“Ìwọ Náfítánì, Náfítánì kún fún ojú rere Ọlọ́runàti ìbùkún Olúwa;yóò jogún ìhà ìwọ̀ oòrùn àti gúṣù.”
24 Ní ti Áṣérì ó wí pé:“Ìbùkún ọmọ ni ti Áṣérì;jẹ́ kí ó rí ojú rere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀kí ó sì ri ẹṣẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
25 Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ,agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.