41 Mósè sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
42 Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrin yín. Ki á má baà lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀ta yín.
43 Nítorí pé àwọn ará Ámélékì àti àwọn ará Kénánì yóò kojú yín níbẹ̀. Nítorí pé Ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
44 Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láì jẹ́ pé àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú Olúwa tàbí Mósè kúrò nínú ibùdó.
45 Àwọn ará Ámálékì àti àwọn ará Kénánì tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Hómà.