16 Olúwa pàdé Bálámù ó sì fí ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Bálákì kí o sì jísẹ́ fún un.”
17 Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì báà tí ó dúró sí ẹ̀gbẹ́ ẹbọ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Móábù. Bálákì sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”
18 Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ:“Dìde, Bálákì;kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sípórà.
19 Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́,tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà.Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é?Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu-un ṣẹ?
20 Èmi gba àṣẹ láti bùkún;Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.
21 “Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jákọ́bù,kò sì rí búburú kankan nínú Ísírẹ́lì. Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn.Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
22 Ọlọ́run mú wọn jáde láti Éjíbítì wá,wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.