17 Wọ́n tún bẹ̀rẹ̀ sí rúbọ sí àwọn ẹ̀mí burúkú,Àwọn oriṣa tí wọn kò mọ̀ rí,tí àwọn baba wọn kò sì bọ rí.
18 Ẹ gbàgbé àpáta ìgbàlà yín,ẹ gbàgbé Ọlọrun tí ó da yín.
19 “Nígbà tí OLUWA rí ohun tí àwọn ọmọ rẹ̀ ń ṣe,ó kọ̀ wọ́n sílẹ̀,nítorí pé, wọ́n mú un bínú.
20 Ó ní, ‘N óo mójú kúrò lára wọn,n óo sì máa wò bí ìgbẹ̀yìn wọn yóo ti rí.Nítorí olóríkunkun ni wọ́n,àwọn alaiṣootọ ọmọ!
21 Nítorí oriṣa lásánlàsàn,wọn sọ èmi Ọlọrun di òjòwú;wọn sì ti fi àwọn ère wọn mú mi bínú.Nítorí náà, èmi náà óo lo àwọn eniyan lásánlàsànláti mu àwọn náà jowú,n óo sì lo aṣiwèrè orílẹ̀-èdè lásánlàsàn kanláti mú wọn bínú.
22 Nítorí iná ibinu mi ń jó,yóo sì jó títí dé isà òkú.Yóo jó ayé ati ohun gbogbo tí ń bẹ ninu rẹ̀ ní àjórun,tó fi mọ́ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá.
23 “ ‘N óo da oríṣìíríṣìí ibi sórí wọn,n óo sì rọ òjò ọfà mi sára wọn.