1 OLUWA sọ fún Mose pé,
2 “Fìyà jẹ àwọn ará Midiani fún ohun tí wọ́n ṣe sí àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn náà, o óo kú.”
3 Mose bá sọ fún àwọn eniyan náà pé, “Ẹ múra ogun kí á lè gbógun ti àwọn ará Midiani, kí á sì fìyà jẹ wọ́n fún ohun tí wọ́n ṣe sí OLUWA.
4 Ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan yóo mú ẹgbẹrun eniyan wá fún ogun náà.”
5 Nítorí náà láàrin ẹgbẹẹgbẹrun àwọn ọmọ Israẹli, ẹgbaafa (12,000) ọkunrin ni wọ́n dájọ láti lọ sójú ogun, ẹgbẹẹgbẹrun láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
6 Mose sì rán wọn lọ sójú ogun lábẹ́ àṣẹ Finehasi ọmọ Eleasari alufaa, pẹlu àwọn ohun èlò mímọ́ ati fèrè fún ìdágìrì lọ́wọ́ rẹ̀.
7 Wọ́n gbógun ti àwọn ará Midiani gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti pàṣẹ fún Mose, wọ́n sì pa gbogbo àwọn ọkunrin wọn.