16 Dani yio ma ṣe idajọ awọn enia rẹ̀, bi ọkan ninu awọn ẹ̀ya Israeli.
17 Dani yio dabi ejò li ẹba ọ̀na, bi paramọlẹ li ọ̀na, ti ibù ẹṣin ṣán ni gigĩsẹ, tòbẹ̃ ti ẹniti o gùn u yio fi ṣubu sẹhin.
18 Emi ti duro dè ìgbala rẹ, OLUWA!
19 Gadi ọwọ́-ogun ni yio kọlù u: ṣugbọn on lé wọn.
20 Lati inu Aṣeri wá onjẹ rẹ̀ yio lọrá, on o si ma mú adidùn ọba wá.
21 Naftali li abo-agbọnrin ti o le sare: o funni li ọ̀rọ rere.
22 Josefu li ẹka eleso pupọ̀, ẹka eleso pupọ̀ li ẹba kanga; ẹtun ẹniti o yọ si ori ogiri.