8 “Mú ọ̀pá, náà kí o sì pe ìjọ àwọn ènìyàn jọ, ìwọ àti Árónì arákùnrin rẹ, kí ẹ sọ̀rọ̀ sí àpáta náà ní ójú wọn, yóò sì tú omi rẹ̀ jáde ìwọ ó sì fún ìjọ àti ẹran wọn mu”
9 Báyìí ni Mósè mú ọ̀pá láti iwájú Olúwa wá, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ fún un.
10 Òun àti Árónì pe àwọn ènìyàn jọ sí ojú kan níwájú àpáta, Mósè sì sọ fún wọn, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yín ọlọ̀tẹ̀, àwa kì yóò lè mú omi jáde láti inú àpáta yìí wá bí?”
11 Nígbà náà ni Mósè gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ó sì fi ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ lu àpáta lẹ́ẹ̀méjì. Omi sì tú jáde, gbogbo ìjọ ènìyàn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sì mu.
12 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Mósè àti Árónì pé, “Nítorí pé ẹ̀yin kò gbà mí gbọ́ tó láti bu ọlá fún mi níwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ìwọ kò ní kó àwọn ìjọ ènìyàn yìí dé ilẹ̀ tí mo fún wọn.”
13 Èyí ni omi ti Méríbà, níbi tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti bá Olúwa jà àti ibi tí O ti fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni mímọ́ láàrin wọn.
14 Mósè sì ránṣẹ́ láti Kádésì sí ọba Édómù, wí pé:“Èyí ni nǹkan tí arákùnrin rẹ Ísírẹ́lì sọ: Ìwọ ti mọ̀ nípa gbogbo ìnira, tí ó wá sí orí wa.