3 Nígbà tí ìwà òmùgọ̀ bá kó ìparun bá a,ọkàn rẹ̀ a máa bá OLUWA bínú.
4 Ọrọ̀ a máa mú kí eniyan ní ọpọlọpọ ọ̀rẹ́ titun,ṣugbọn àwọn ọ̀rẹ́ talaka a máa kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
5 Ẹlẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà,bẹ́ẹ̀ ni òpùrọ́ kò ní bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀san ibi.
6 Ọ̀pọ̀ eniyan níí máa ń wá ojurere ẹni tó lawọ́,gbogbo eniyan sì ni ọ̀rẹ́ ẹni tí ń fúnni lẹ́bùn.
7 Gbogbo àwọn arakunrin talaka ni wọ́n kórìíra rẹ̀,kí á má ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tí wọ́n jìnnà sí i!Ó fọ̀rọ̀ ẹnu fà wọ́n títí, sibẹ wọn kò súnmọ́ ọn.
8 Ẹni tí ó ní ọgbọ́n fẹ́ràn ara rẹ̀,ẹni tí ó bá sì ní òye, yóo ṣe rere.
9 Ẹlẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà,ẹni tí ó ń pa irọ́ yóo parun.