Ìwé Òwe 29 BM

1 Ẹni tí à ń báwí tí ó ń ṣoríkunkun,yóo parun lójijì láìsí àtúnṣe.

2 Nígbà tí olódodo bá di eniyan pataki,àwọn eniyan a máa yọ̀,ṣugbọn nígbà tí eniyan burúkú bá wà lórí oyè,àwọn eniyan a máa kérora.

3 Ọlọ́gbọ́n ọmọ a máa mú inú baba rẹ̀ dùn,ṣugbọn ẹni tí ń tẹ̀lé aṣẹ́wó kiri, ń fi ọrọ̀ ara rẹ̀ ṣòfò.

4 Ọba tí ó bá ń ṣe ìdájọ́ òdodo, a máa fìdí orílẹ̀-èdè múlẹ̀,ṣugbọn ọba onírìbá a máa dojú orílẹ̀-èdè bolẹ̀.

5 Ẹni tí ó bá ń pọ́n aládùúgbò rẹ̀,ń dẹ àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ̀.

6 Eniyan burúkú bọ́ sinu àwọ̀n ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,ṣugbọn olódodo lè kọrin, ó sì lè máa yọ̀.

7 Olódodo a máa bìkítà fún ẹ̀tọ́ àwọn talaka,ṣugbọn àwọn eniyan burúkú kò ní òye irú rẹ̀.

8 Àwọn ẹlẹ́gàn a máa dá rúkèrúdò sílẹ̀ láàrin ìlú,ṣugbọn àwọn ọlọ́gbọ́n a máa paná ibinu.

9 Nígbà tí ọlọ́gbọ́n bá pe òmùgọ̀ lẹ́jọ́,ẹ̀rín ni òmùgọ̀ yóo máa fi rín,yóo máa pariwo, kò sì ní dákẹ́.

10 Àwọn apànìyàn kórìíra olóòótọ́ inú,wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa á.

11 Òmùgọ̀ eniyan a máa bínú,ṣugbọn ọlọ́gbọ́n a máa mú sùúrù.

12 Bí aláṣẹ bá ń fetí sí irọ́,gbogbo àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ yóo di eniyankeniyan.

13 Ohun tí ó sọ talaka ati aninilára di ọ̀kan náà ni pé,OLUWA ló fún àwọn mejeeji ní ojú láti ríran.

14 Ọba tí ó dájọ́ ẹ̀tọ́ fún talaka,ní a óo fìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ títí.

15 Pàṣán ati ìbáwí a máa kọ́ ọmọ lọ́gbọ́n,ọmọ tí a bá fi sílẹ̀ yóo dójúti ìyá rẹ̀.

16 Nígbà tí eniyan burúkú bá wà lórí oyè, ẹ̀ṣẹ̀ a máa pọ̀ síi,ṣugbọn lójú olódodo ni wọn yóo ti ṣubú.

17 Tọ́ ọmọ rẹ, yóo sì fún ọ ní ìsinmi,yóo sì mú inú rẹ dùn.

18 Orílẹ̀-èdè tí kò bá ní ìfihàn láti ọ̀run, yóo dàrú,ṣugbọn ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń pa òfin mọ́.

19 Ọ̀rọ̀ ẹnu nìkan kò tó láti fi bá ẹrú wí,ó lè fi etí gbọ́ ṣugbọn kí ó má ṣe ohunkohun.

20 Òmùgọ̀ nírètí ju ẹni tí yóo sọ̀rọ̀ sọ̀rọ̀,tí kò lè kó ara rẹ̀ ní ìjánu lọ.

21 Bí eniyan bá kẹ́ ẹrú ní àkẹ́jù,yóo ya ìyàkuyà níkẹyìn.

22 Ẹni tí inú ń bí a máa dá rògbòdìyàn sílẹ̀,onínúfùfù a sì máa ṣe ọpọlọpọ àṣìṣe.

23 Ìgbéraga eniyan a máa rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀,ṣugbọn onírẹ̀lẹ̀ ọkàn yóo gba iyì.

24 Ẹni tí ó ṣe alábàápín pẹlu olè kò fẹ́ràn ẹ̀mí ara rẹ̀,ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ègún, ṣugbọn kò sọ fún ẹnikẹ́ni.

25 Ìbẹ̀rù eniyan a máa di ìdẹkùn fún eniyan,ṣugbọn ẹni bá gbẹ́kẹ̀lé OLUWA yóo wà láìléwu.

26 Ọ̀pọ̀ ń wá ojurere olórí,ṣugbọn OLUWA níí dáni ní ẹjọ́ òdodo.

27 Olódodo a máa kórìíra alaiṣootọ,eniyan burúkú a sì kórìíra eniyan rere.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24 25 26 27 28 29 30 31