Ìwé Òwe 25 BM

Àwọn Òwe Mìíràn tí Solomoni Pa

1 Àwọn òwe mìíràn tí Solomoni pa,tí àwọn òṣìṣẹ́ Hesekaya ọba Juda kọ sílẹ̀ nìwọ̀nyí.

2 Ògo ni ó jẹ́ fún Ọlọrun láti fi nǹkan pamọ́,ṣugbọn ògo ló sá tún jẹ́ fún ọbaláti wádìí nǹkan ní àwárí.

3 Bí ọ̀run ti ga, tí ilẹ̀ sì jìn,bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò lè mọ ohun tí ó wà lọ́kàn àwọn ọba.

4 Yọ́ gbogbo ìdọ̀tí tí ó wà lára fadaka kúrò,alágbẹ̀dẹ yóo sì rí fadaka fi ṣe ohun èlò.

5 Mú àwọn olùdámọ̀ràn ibi kúrò lọ́dọ̀ ọba,a óo sì fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ pẹlu òdodo.

6 Má ṣe gbéraga níwájú ọba,tabi kí o jókòó ní ipò àwọn eniyan pataki,

7 nítorí ó sàn kí ó wí fún ọ pé,“Máa bọ̀ lókè níhìn-ín”,jù pé kí ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ níwájú ọlọ́lá kan lọ.

8 Má fi ìwàǹwára fa ẹnikẹ́ni lọ sílé ẹjọ́,nítorí kí ni o óo ṣe nígbà tí aládùúgbò rẹ bá dójútì ọ́.

9 Bí o bá ń bá aládùúgbò rẹ ṣe àríyànjiyànmá ṣe tú àṣírí ẹlòmíràn,

10 kí ẹni tí ó bá gbọ́ má baà dójútì ọ́,kí o má baà sọ ara rẹ lórúkọ.

11 Ọ̀rọ̀ tí a sọ lákòókò tí ó yẹdàbí ohun ọ̀ṣọ́ wúrà tí a gbé sinu àwo fadaka.

12 Ìbáwí ọlọ́gbọ́n dàbí òrùka wúrà,tabi ohun ọ̀ṣọ́ tí a fi wúrà ṣe,fún ẹni tí ó ní etí láti fi gbọ́.

13 Bí òtútù yìnyín nígbà ìkórè,bẹ́ẹ̀ ni olóòótọ́ iranṣẹ jẹ́, sí àwọn tí ó rán an,a máa fi ọkàn àwọn oluwa rẹ̀ balẹ̀.

14 Bí òjò tí ó ṣú dudu tí ó fẹ́ atẹ́gùn títíṣugbọn tí kò rọ̀,ni ẹni tí ó ń fọ́nnu láti fúnni lẹ́bùn,tí kò sì fúnni ní nǹkankan.

15 Pẹlu sùúrù, a lè yí aláṣẹ lọ́kàn padaọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́ sì lè fọ́ eegun.

16 Bí o bá rí oyin, lá a níwọ̀nba,má lá a ní àlájù, kí o má baà bì.

17 Má máa lọ sílé aládùúgbò rẹ lemọ́lemọ́,kí ọ̀rọ̀ rẹ má baà sú u, kí ó sì kórìíra rẹ.

18 Ẹni tí ó jẹ́rìí èké nípa aládùúgbò rẹ̀dàbí kùmọ̀ ọmọ ogun, tabi idà, tabi ọfà tí ó mú.

19 Igbẹkẹle ninu alaiṣootọ ní àkókò ìṣòro,dàbí eyín tí ń ro ni, tabi ẹsẹ̀ tí ó rọ́.

20 Bí ẹni tí a bọ́ṣọ rẹ̀ ninu òtútù,tabi tí a da ọtí kíkan sójú egbò rẹ̀,ni ẹni tí à ń kọrin fún ní àkókò tí inú rẹ̀ bàjẹ́.

21 Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ, fún un ní oúnjẹ jẹ,bí òùngbẹ bá ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mu.

22 Nípa bẹ́ẹ̀ o óo wa ẹ̀yinná lé e lórí,OLUWA yóo sì san ẹ̀san rere fún ọ.

23 Bí ẹ̀fúùfù ìhà àríwá tíí mú òjò wá,bẹ́ẹ̀ ni òfófó ṣíṣe máa ń fa kí a máa fi ojú burúkú woni.

24 Ó sàn kí á máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà,ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ.

25 Gẹ́gẹ́ bí omi tútù ti rí fún ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ,ni ìròyìn ayọ̀ láti ilẹ̀ òkèèrè rí.

26 Olódodo tí ó fi ààyè sílẹ̀ fún eniyan burúkúdàbí odò tí omi rẹ̀ dàrútabi kànga tí a da ìdọ̀tí sí.

27 Kò dára kí eniyan lá oyin ní àlájù,bẹ́ẹ̀ ni kò dára kí eniyan máa wá iyì ní àwájù.

28 Ẹni tí kò lè kó ara rẹ̀ níjàánu,dàbí ìlú tí ọ̀tá wọ̀,tí wọ́n sì wó odi rẹ̀ lulẹ̀.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24 25 26 27 28 29 30 31