17 Tọ́ ọmọ rẹ, yóo sì fún ọ ní ìsinmi,yóo sì mú inú rẹ dùn.
18 Orílẹ̀-èdè tí kò bá ní ìfihàn láti ọ̀run, yóo dàrú,ṣugbọn ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń pa òfin mọ́.
19 Ọ̀rọ̀ ẹnu nìkan kò tó láti fi bá ẹrú wí,ó lè fi etí gbọ́ ṣugbọn kí ó má ṣe ohunkohun.
20 Òmùgọ̀ nírètí ju ẹni tí yóo sọ̀rọ̀ sọ̀rọ̀,tí kò lè kó ara rẹ̀ ní ìjánu lọ.
21 Bí eniyan bá kẹ́ ẹrú ní àkẹ́jù,yóo ya ìyàkuyà níkẹyìn.
22 Ẹni tí inú ń bí a máa dá rògbòdìyàn sílẹ̀,onínúfùfù a sì máa ṣe ọpọlọpọ àṣìṣe.
23 Ìgbéraga eniyan a máa rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀,ṣugbọn onírẹ̀lẹ̀ ọkàn yóo gba iyì.