11 Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìtọ́ni OLUWA, má sì ṣe jẹ́ kí ìbáwí rẹ̀ sú ọ.
12 Nítorí ẹni tí OLUWA bá fẹ́ níí báwí gẹ́gẹ́ bí baba tí máa ń bá ọmọ rẹ̀ tí ó bá fẹ́ràn wí.
13 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó wá ọgbọ́n rí,ati ẹni tí ó ní òye.
14 Nítorí èrè rẹ̀ dáraju èrè orí fadaka ati ti wúrà lọ.
15 Ọgbọ́n níye lóríó ju ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye lọ,kò sí ohun tí o lè fi wé e,ninu gbogbo ohun tí ọkàn rẹ lè fẹ́.
16 Ẹ̀mí gígùn wà ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀,ọrọ̀ ati iyì sì wà ní ọwọ́ òsì rẹ̀.
17 Ọ̀nà rẹ̀ tura pupọ,alaafia sì ni gbogbo ọ̀nà rẹ̀.