5 Fi tọkàntọkàn gbẹ́kẹ̀lé OLUWA,má sì tẹ̀lé ìmọ̀ ara rẹ.
6 Mọ Ọlọrun ní gbogbo ọ̀nà rẹ,yóo sì mú kí ọ̀nà rẹ tọ́.
7 Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara rẹ, bẹ̀rù OLUWA, kí o sì yẹra fún ibi.
8 Tí o bá ṣe bẹ́ẹ̀, yóo jẹ́ ìwòsàn fún ara rẹ,ati ìtura fún egungun rẹ.
9 Fi ohun ìní rẹ bọ̀wọ̀ fún OLUWApẹlu gbogbo àkọ́so oko rẹ.
10 Nígbà náà ni àká rẹ yóo kún bámúbámú,ìkòkò waini rẹ yóo sì kún àkúnya.
11 Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìtọ́ni OLUWA, má sì ṣe jẹ́ kí ìbáwí rẹ̀ sú ọ.