11 Ọkọ rẹ̀ yóo fi tọkàntọkàn gbẹ́kẹ̀lé e,kò sì ní ṣaláì ní ohunkohun.
12 Rere ni obinrin náà máa ń ṣe fún unkò ní ṣe é níbi, ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
13 A máa lọ wá irun aguntan ati òwú ìhunṣọ,a sì máa fi tayọ̀tayọ̀ hun aṣọ.
14 Obinrin náà dàbí ọkọ̀ ojú omi oníṣòwò,tí ó ń mú oúnjẹ wálé láti ọ̀nà jíjìn réré.
15 Ìdájí níí tií jí láti wá oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀,ati láti yan iṣẹ́ fún àwọn iranṣẹbinrin rẹ̀.
16 Bí ó bá rí ilẹ̀ oko, a yẹ̀ ẹ́ wò, a sì rà á,a sì fi èrè iṣẹ́ rẹ̀ gbin ọgbà àjàrà.
17 A fi agbára fún ọ̀já mọ́nú,a sì tẹpá mọ́ṣẹ́.