16 Bí ó bá rí ilẹ̀ oko, a yẹ̀ ẹ́ wò, a sì rà á,a sì fi èrè iṣẹ́ rẹ̀ gbin ọgbà àjàrà.
17 A fi agbára fún ọ̀já mọ́nú,a sì tẹpá mọ́ṣẹ́.
18 A máa mójútó ọjà tí ó ń tà,fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú lóru.
19 Ó fi ọwọ́ lé kẹ̀kẹ́ òwú,ó sì ń ran òwú.
20 Ó lawọ́ sí àwọn talaka,a sì máa ran àwọn aláìní lọ́wọ́.
21 Kì í bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nígbà òtútù,nítorí gbogbo wọn ni ó ti bá hun aṣọ tí ó móoru.
22 A máa hun aṣọ ọlọ́nà a sì fi bo ibùsùn rẹ̀,òun náà á wọ aṣọ funfun dáradára ati ti elése àlùkò.