20 Ọmọ mi, fetí sí ọ̀rọ̀ mi,tẹ́tí sílẹ̀ sí ohun tí mò ń sọ.
21 Má jẹ́ kí wọn rú ọ lójú,fi wọ́n sọ́kàn.
22 Nítorí pé ìyè ni wọ́n jẹ́ fún àwọn tí ó rí wọn,ati ìwòsàn fún gbogbo ẹran ara wọn.
23 Ṣọ́ra pẹlu èrò ọkàn rẹ,nítorí èrò ọkàn ni orísun ìyè.
24 Má lọ́wọ́ ninu ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ,sì jìnnà sí ọ̀rọ̀ àgàbàgebè.
25 Jẹ́ kí ojú rẹ máa wo ọ̀kánkán,kí o sì kọjú sí ibi tí ò ń lọ tààrà.
26 Kíyèsí ìrìn ẹsẹ̀ rẹ,gbogbo ọ̀nà rẹ yóo sì là.