8 Gbé ọgbọ́n lárugẹ, yóo sì gbé ọ ga,yóo bu ọlá fún ọ, bí o bá gbà á mọ́ra.
9 Yóo fi nǹkan ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà bò ọ́ lórí,yóo sì dé ọ ní adé dáradára.”
10 Gbọ́, ọmọ mi, gba ẹ̀kọ́ mi,kí ẹ̀mí rẹ lè gùn.
11 Mo ti kọ́ ọ ní ọgbọ́n,mo sì ti fẹsẹ̀ rẹ lé ọ̀nà òtítọ́.
12 Nígbà tí o bá ń rìn, o kò ní rí ìdínà,nígbà tí o bá ń sáré, o kò ní fi ẹsẹ̀ kọ.
13 Di ẹ̀kọ́ mú ṣinṣin,má jẹ́ kí ó bọ́,pa á mọ́, nítorí òun ni ìyè rẹ.
14 Má ṣe gba ọ̀nà ẹni ibi,má sì ṣe rin ọ̀nà eniyan burúkú.