11 nítorí ọgbọ́n níye lórí ju ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye lọ,kò sí ohun tí o fẹ́, tí a lè fi wé e.
12 Èmi, ọgbọ́n, òye ni mò ń bá gbélé,mo ṣe àwárí ìmọ̀ ati làákàyè.
13 Ẹni tó bá bẹ̀rù OLUWA, yóo kórìíra ibi,mo kórìíra ìwà ìgbéraga, ọ̀nà ibi ati ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́.
14 Èmi ni mo ní ìmọ̀ràn ati ọgbọ́n tí ó yè kooro,mo sì ní òye ati agbára.
15 Nípasẹ̀ mi ni àwọn ọba fi ń ṣe ìjọba,tí àwọn alákòóso sì ń pàṣẹ òdodo.
16 Nípasẹ̀ mi ni àwọn olórí ń ṣe àkóso,gbogbo àwọn ọlọ́lá sì ń ṣe àkóso ayé.
17 Mo fẹ́ràn gbogbo àwọn tí wọ́n fẹ́ràn mi,àwọn tí wọ́n bá fi tọkàntọkàn wá mi yóo sì rí mi.