Kronika Keji 23:12-18 BM

12 Nígbà tí Atalaya gbọ́ híhó àwọn eniyan, ati bí wọ́n ti ń sá kiri tí wọ́n sì ń yin ọba, ó lọ sí ilé OLUWA níbi tí àwọn eniyan péjọ sí,

13 ó rí i tí ọba náà dúró lẹ́bàá òpó lẹ́nu ọ̀nà, àwọn ọ̀gágun ati àwọn tí wọn ń fọn fèrè dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Gbogbo eniyan ń hó ìhó ayọ̀, wọ́n ń fọn fèrè, àwọn tí ń lo ohun èlò orin ń fi wọ́n kọrin, àwọn eniyan sì ń gberin. Nígbà tí Atalaya rí nǹkan tí ń ṣẹlẹ̀, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ẹ̀rù bà á, ó sì kígbe lóhùn rara pé, “Ọ̀tẹ̀ nìyí! Ọ̀tẹ̀ nìyí!”

14 Jehoiada bá rán àwọn ọ̀gágun ọmọ ogun ọgọrun-un pé, “Ẹ fà á síta láàrin àwọn ọmọ ogun, ẹni tí ó bá tẹ̀lé e, ẹ pa á.” Nítorí àwọn alufaa ní kí wọ́n má pa á ninu tẹmpili OLUWA.

15 Wọ́n bá mú un lọ sí ẹnu ọ̀nà Ẹṣin, ní ààfin, wọ́n sì pa á sibẹ.

16 Jehoiada bá àwọn eniyan náà dá majẹmu pẹlu ọba, pé ti OLUWA ni àwọn yóo máa ṣe.

17 Lẹ́yìn náà, gbogbo wọn lọ sí ilé oriṣa Baali, wọ́n wó o palẹ̀, wọ́n wó pẹpẹ ati àwọn ère túútúú, wọ́n sì pa Matani, tí ó jẹ́ alufaa Baali, níwájú pẹpẹ.

18 Jehoiada yan àwọn aṣọ́nà fún ilé OLUWA, lábẹ́ àkóso àwọn alufaa, ọmọ Lefi, ati àwọn ọmọ Lefi tí Dafidi ti ṣètò láti máa rú ẹbọ sísun sí OLUWA bí a ti kọ ọ́ sinu ìwé òfin Mose, pẹlu àjọyọ̀ ati orin, gẹ́gẹ́ bí Dafidi ti ṣètò.