9 Nígbà tí ọlọ́gbọ́n bá pe òmùgọ̀ lẹ́jọ́,ẹ̀rín ni òmùgọ̀ yóo máa fi rín,yóo máa pariwo, kò sì ní dákẹ́.
10 Àwọn apànìyàn kórìíra olóòótọ́ inú,wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
11 Òmùgọ̀ eniyan a máa bínú,ṣugbọn ọlọ́gbọ́n a máa mú sùúrù.
12 Bí aláṣẹ bá ń fetí sí irọ́,gbogbo àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ yóo di eniyankeniyan.
13 Ohun tí ó sọ talaka ati aninilára di ọ̀kan náà ni pé,OLUWA ló fún àwọn mejeeji ní ojú láti ríran.
14 Ọba tí ó dájọ́ ẹ̀tọ́ fún talaka,ní a óo fìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ títí.
15 Pàṣán ati ìbáwí a máa kọ́ ọmọ lọ́gbọ́n,ọmọ tí a bá fi sílẹ̀ yóo dójúti ìyá rẹ̀.