10 Gba ẹ̀kọ́ mi dípò fadaka,ati ìmọ̀ dípò ojúlówó wúrà,
11 nítorí ọgbọ́n níye lórí ju ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye lọ,kò sí ohun tí o fẹ́, tí a lè fi wé e.
12 Èmi, ọgbọ́n, òye ni mò ń bá gbélé,mo ṣe àwárí ìmọ̀ ati làákàyè.
13 Ẹni tó bá bẹ̀rù OLUWA, yóo kórìíra ibi,mo kórìíra ìwà ìgbéraga, ọ̀nà ibi ati ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́.
14 Èmi ni mo ní ìmọ̀ràn ati ọgbọ́n tí ó yè kooro,mo sì ní òye ati agbára.
15 Nípasẹ̀ mi ni àwọn ọba fi ń ṣe ìjọba,tí àwọn alákòóso sì ń pàṣẹ òdodo.
16 Nípasẹ̀ mi ni àwọn olórí ń ṣe àkóso,gbogbo àwọn ọlọ́lá sì ń ṣe àkóso ayé.