12 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn olórí àlùfàà àti àwọn àgbààgbà Júù fi gbogbo ẹ̀sùn wọn kàn án, Jésù kò dáhùn kan.
13 Nígbà náà ni Pílátù, béèrè lọ́wọ́ Jésù pé, “Àbí ìwọ kò gbọ́ ẹ̀rí tí wọn ń wí nípa rẹ ni?”
14 Jésù kò sì tún dáhùn kan. Èyí sì ya Baálẹ̀ lẹ́nu.
15 Ó jẹ́ àṣà Baálẹ̀ láti dá ọ̀kan nínú àwọn ẹlẹ́wọ̀n Júù sílẹ̀ lọ́dọọdún, ní àsìkò àjọ̀dún ìrékọjá. Ẹnikẹ́ni tí àwọn ènìyàn bá ti fẹ́ ni.
16 Ní àsìkò náà ọ̀daràn paraku kan wà nínú ẹ̀wọ̀n tí à ń pè Bárábbà.
17 Bí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti pé jọ ṣíwájú ilé Pílátù lówúrọ̀ ọjọ́ náà, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ta ni ẹ̀yin ń fẹ́ kí n dá sílẹ̀ fún yín, Bárábbà tàbí Jésù, ẹni tí ń jẹ́ Kírísítì?”
18 Òun ti mọ̀ pé nítorí ìlara ni wọn fi fà á lé òun lọ́wọ́,;