Kronika Kinni 11:17-23 BM

17 Dafidi ranti ilé, ó ní, “Kì bá ti dùn tó kí n rí ẹni fún mi ní omi mu láti inú kànga tí ó wà lẹ́nu ibodè Bẹtilẹhẹmu!”

18 Àwọn akọni mẹta náà bá la àgọ́ àwọn ọmọ ogun Filistia já, dé ibi kànga náà, wọ́n sì bu omi náà wá fún Dafidi. Ṣugbọn ó kọ̀, kò mu ún; kàkà bẹ́ẹ̀, ó tú u sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fún OLUWA.

19 Ó ní, “Kí á má rí i pé mo ṣe nǹkan yìí níwájú Ọlọrun mi. Ǹjẹ́ ó yẹ kí n mu ẹ̀jẹ̀ àwọn ọkunrin wọnyi?” Nítorí pé ẹ̀mí wọn ni wọ́n fi wéwu kí wọn tó rí omi yìí bù wá; nítorí náà ni ó ṣe kọ̀, tí kò sì mu ún. Ó jẹ́ ohun ìgboyà tí àwọn akọni mẹta náà ṣe.

20 Abiṣai, arakunrin Joabu, ni olórí àwọn ọgbọ̀n ọ̀gágun. Ó fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ pa ọọdunrun eniyan, nípa bẹ́ẹ̀ òkìkí tirẹ̀ náà súnmọ́ ti àwọn akọni mẹta náà.

21 Òun ni ó lókìkí jùlọ ninu àwọn ọgbọ̀n ọ̀gágun náà, ó sì di olórí wọn; ṣugbọn kò ní òkìkí tó àwọn akọni mẹta.

22 Bẹnaya, ọmọ Jehoiada, láti ìlú Kabiseeli, jẹ́ ọmọ ogun tí ó ti ṣe ọpọlọpọ ohun ìyanu, ó pa àwọn abàmì eniyan meji ará Moabu. Ó wọ ihò lọ pa kinniun kan ní ọjọ́ kan tí yìnyín bo ilẹ̀.

23 Ó pa ará Ijipti kan tí ó ga ju mita meji lọ. Ará Ijipti náà gbé ọ̀kọ̀ tí ó tóbi lọ́wọ́. Ṣugbọn kùmọ̀ ni Bẹnaya mú lọ́wọ́ lọ bá a, ó gba ọ̀kọ̀ tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì fi pa á.