Kronika Kinni 11 BM

Dafidi Jọba lórí Israẹli ati Juda

1 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli bá parapọ̀, wọ́n wá sọ́dọ̀ Dafidi ní Heburoni, wọ́n ní, “Wò ó, ẹ̀jẹ̀ kan náà ni gbogbo wa pẹlu rẹ.

2 Látẹ̀yìnwá, nígbà tí Saulu pàápàá wà lórí oyè, ìwọ ni ò ń ṣáájú Israẹli lójú ogun. OLUWA Ọlọrun rẹ sì ti ṣèlérí fún ọ pé ìwọ ni o óo máa ṣe olùṣọ́ àwọn ọmọ Israẹli, eniyan òun, tí o óo sì jọba lé wọn lórí.”

3 Nítorí náà, àwọn àgbààgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ Dafidi ọba, ní Heburoni. Dafidi sì bá wọn dá majẹmu níbẹ̀ níwájú OLUWA. Wọ́n fi òróró yàn án ní ọba lórí Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ OLUWA láti ẹnu Samuẹli.

4 Dafidi ati àwọn ọmọ Israẹli lọ gbógun ti ìlú Jerusalẹmu, (Jebusi ni orúkọ Jerusalẹmu nígbà náà, ibẹ̀ ni àwọn ará Jebusi ń gbé.)

5 Àwọn ará Jebusi sọ fún Dafidi pé, “O ò ní wọ ìlú yìí.” Ṣugbọn Dafidi ṣẹgun ibi ààbò Sioni, tí à ń pè ní ìlú Dafidi.

6 Dafidi ní, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ́kọ́ pa ará Jebusi kan ni yóo jẹ́ balogun fún àwọn ọmọ ogun mi.” Joabu, ọmọ Seruaya ni ó kọ́kọ́ lọ, ó sì di balogun.

7 Dafidi lọ ń gbé ibi ààbò náà, nítorí náà ni wọ́n ṣe ń pe ibẹ̀ ní ìlú Dafidi.

8 Ó tún ìlú náà kọ́ yípo, bẹ̀rẹ̀ láti Milo, ibi tí a ti kun ilẹ̀ náà yíká. Joabu sì parí èyí tí ó kù.

9 Dafidi bẹ̀rẹ̀ sí di alágbára sí i, nítorí pé OLUWA àwọn ọmọ ogun wà pẹlu rẹ̀.

Àwọn Ọmọ Ogun Dafidi tí Wọ́n Jẹ́ Olókìkí

10 Àwọn tí wọ́n jẹ́ olórí ninu àwọn akọni ọmọ ogun Dafidi nìwọ̀nyí; àwọn ni wọ́n fọwọsowọpọ pẹlu àwọn ọmọ Israẹli, láti fi Dafidi jọba, tí wọ́n sì fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìlérí tí OLUWA ti ṣe fún Israẹli.

11 Àkọsílẹ̀ orúkọ wọn nìyí: Jaṣobeamu láti ìdílé Hakimoni ni olórí àwọn ọ̀gágun olókìkí mẹta. Òun ni ó fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ pa ọọdunrun (300) eniyan ninu ogun kan ṣoṣo.

12 Ẹni tí ó tẹ̀lé e ninu àwọn ọ̀gágun olókìkí mẹta náà ni Eleasari ọmọ Dodo ará Aho.

13 Ó wà pẹlu Dafidi nígbà tí Dafidi bá àwọn ará Filistia jagun ní Pasi Damimu, wọ́n wà ninu oko ọkà baali kan nígbà tí àwọn ọmọ ogun Israẹli bẹ̀rẹ̀ sí sá fún àwọn ará Filistia.

14 Ṣugbọn òun ati àwọn eniyan rẹ̀ dúró gbọningbọnin ninu oko náà, wọ́n bá àwọn ará Filistia jà. OLUWA gbà wọ́n, ó sì fún wọn ní ìṣẹ́gun ńlá.

15 Ní ọjọ́ kan, mẹta ninu àwọn ọgbọ̀n ọ̀gágun olókìkí lọ sọ́dọ̀ Dafidi nígbà tí ó wà ní ihò Adulamu, nígbà tí àwọn ọmọ ogun Filistini dó sí àfonífojì Refaimu.

16 Ibi ààbò ni Dafidi wà nígbà náà, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ogun Filistini sì ti wọ Bẹtilẹhẹmu,

17 Dafidi ranti ilé, ó ní, “Kì bá ti dùn tó kí n rí ẹni fún mi ní omi mu láti inú kànga tí ó wà lẹ́nu ibodè Bẹtilẹhẹmu!”

18 Àwọn akọni mẹta náà bá la àgọ́ àwọn ọmọ ogun Filistia já, dé ibi kànga náà, wọ́n sì bu omi náà wá fún Dafidi. Ṣugbọn ó kọ̀, kò mu ún; kàkà bẹ́ẹ̀, ó tú u sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fún OLUWA.

19 Ó ní, “Kí á má rí i pé mo ṣe nǹkan yìí níwájú Ọlọrun mi. Ǹjẹ́ ó yẹ kí n mu ẹ̀jẹ̀ àwọn ọkunrin wọnyi?” Nítorí pé ẹ̀mí wọn ni wọ́n fi wéwu kí wọn tó rí omi yìí bù wá; nítorí náà ni ó ṣe kọ̀, tí kò sì mu ún. Ó jẹ́ ohun ìgboyà tí àwọn akọni mẹta náà ṣe.

20 Abiṣai, arakunrin Joabu, ni olórí àwọn ọgbọ̀n ọ̀gágun. Ó fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ pa ọọdunrun eniyan, nípa bẹ́ẹ̀ òkìkí tirẹ̀ náà súnmọ́ ti àwọn akọni mẹta náà.

21 Òun ni ó lókìkí jùlọ ninu àwọn ọgbọ̀n ọ̀gágun náà, ó sì di olórí wọn; ṣugbọn kò ní òkìkí tó àwọn akọni mẹta.

22 Bẹnaya, ọmọ Jehoiada, láti ìlú Kabiseeli, jẹ́ ọmọ ogun tí ó ti ṣe ọpọlọpọ ohun ìyanu, ó pa àwọn abàmì eniyan meji ará Moabu. Ó wọ ihò lọ pa kinniun kan ní ọjọ́ kan tí yìnyín bo ilẹ̀.

23 Ó pa ará Ijipti kan tí ó ga ju mita meji lọ. Ará Ijipti náà gbé ọ̀kọ̀ tí ó tóbi lọ́wọ́. Ṣugbọn kùmọ̀ ni Bẹnaya mú lọ́wọ́ lọ bá a, ó gba ọ̀kọ̀ tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì fi pa á.

24 Àwọn ohun tí Bẹnaya, ọmọ Jehoiada, ṣe nìyí, tí ó sọ ọ́ di olókìkí, yàtọ̀ sí ti àwọn akọni mẹta tí a sọ nípa wọn.

25 Ó di olókìkí láàrin àwọn ọgbọ̀n ọ̀gágun; ṣugbọn òkìkí tirẹ̀ kò tó ti àwọn akọni mẹta náà. Dafidi bá fi ṣe olórí àwọn tí ń ṣọ́ ọba.

26 Àwọn olókìkí mìíràn ninu àwọn ọmọ ogun Dafidi nìwọ̀nyí: Asaheli, arakunrin Joabu; ati Elihanani, ọmọ Dodo, ará Bẹtilẹhẹmu;

27 Ṣamotu, láti Harodu;

28 Helesi, láti inú ìdílé Peloni, Ira, ọmọ Ikeṣi ará Tekoa, ati Abieseri, láti Anatoti

29 Sibekai, láti inú ìdílé Huṣati, ati Ilai, láti inú ìdílé Aho;

30 Maharai, ará Netofa, ati Helodi, ọmọ Baana, ará Netofa;

31 Itai, ọmọ Ribai, ará Gibea, láti inú ẹ̀yà Bẹnjamini, ati Bẹnaya, ará Piratoni;

32 Hurai, ará etí odò Gaaṣi, ati Abieli, ará Aribati;

33 Asimafeti, ará Bahurumu, ati Eliaba ará Ṣaaliboni;

34 Haṣemu, ará Gisoni, ati Jonatani, ọmọ Ṣagee, ará Harari;

35 Ahiamu, ọmọ Sakari, ará Harari, ati Elifali, ọmọ Uri;

36 Heferi, ará Mekerati, ati Ahija, ará Peloni;

37 Hesiro, ará Kamẹli, ati Naarai ọmọ Esibai;

38 Joẹli, arakunrin Natani, ati Mibihari, ọmọ Hagiri,

39 Seleki, ará Amoni, ati Naharai, ará Beeroti, tí ń ru ihamọra Joabu ọmọ Seruaya.

40 Ira, ará Itiri, ati Garebu ará Itiri,

41 Uraya, ará Hiti, ati Sabadi, ọmọ Ahilai,

42 Adina, ọmọ Ṣisa, láti inú ẹ̀yà Reubẹni, olórí kan láàrin ẹ̀yà Reubẹni, pẹlu ọgbọ̀n àwọn ọmọ ogun rẹ̀;

43 Hanani, ọmọ Maaka, ati Joṣafati, ará Mitini;

44 Usaya, ará Aṣiteratu, Ṣama, ati Jeieli, àwọn ọmọ Hotamu, ará Aroeri,

45 Jediaeli, ọmọ Ṣimiri, ati Joha, arakunrin rẹ̀, ará Tisi,

46 Elieli, ará Mahafi, ati Jẹribai, ati Joṣafia, àwọn ọmọ Elinaamu, ati Itima ará Moabu;

47 Elieli, ati Obedi, ati Jaasieli, ará Mesoba.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24 25 26 27 28 29