Kronika Kinni 19 BM

Dafidi Ṣẹgun Àwọn Ará Amoni ati Àwọn Ará Siria

1 Nígbà tí ó yá, Nahaṣi, ọba àwọn ará Amoni kú, Hanuni ọmọ rẹ̀ sì jọba lẹ́yìn rẹ̀.

2 Dafidi ní, “N óo fi ìfẹ́ hàn sí Hanuni bí baba rẹ̀ ti fi ìfẹ́ hàn sí mi.” Dafidi bá rán oníṣẹ́ lọ kí i kú àṣẹ̀yìndè baba rẹ̀. Àwọn oníṣẹ́ Dafidi bá lọ sọ́dọ̀ Hanuni ní ilẹ̀ Amoni láti bá a kẹ́dùn.

3 Ṣugbọn àwọn ìjòyè ilẹ̀ Amoni sọ fún ọba pé, “Ṣé o rò pé Dafidi ń bọ̀wọ̀ fún baba rẹ ni ó ṣe rán oníṣẹ́ láti wá bá ọ kẹ́dùn? Rárá o. Ó rán wọn láti wá ṣe amí ilẹ̀ yìí ni, kí ó baà lè ṣẹgun rẹ.”

4 Nítorí náà, Hanuni mú àwọn oníṣẹ́ Dafidi, ó fá irùngbọ̀n wọn, ó gé ẹ̀wù wọn ní ìbàdí, ó sì lé wọn jáde.

5 Ojú tì wọ́n pupọ wọn kò lè pada sílé. Nígbà tí Dafidi gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wọn, ó ranṣẹ sí wọn pé kí wọ́n dúró sí Jẹriko títí tí irùngbọ̀n wọn yóo fi hù, lẹ́yìn náà kí wọ́n máa pada bọ̀ wá sílé.

6 Nígbà tí àwọn ará Amoni rí i pé Dafidi ti kórìíra àwọn, Hanuni ati àwọn eniyan rẹ̀ fi ẹgbẹrun (1,000) talẹnti fadaka ranṣẹ sí Mesopotamia, ati sí Aramu-maaka ati sí Soba, láti yá kẹ̀kẹ́ ogun ati àwọn ẹlẹ́ṣin.

7 Wọ́n yá ẹgbaa mẹrindinlogun (32,000) kẹ̀kẹ́ ogun, ati ọba Maaka pẹlu àwọn ọmọ ogun rẹ̀, wọ́n wá, wọ́n sì pàgọ́ ogun wọn sí ẹ̀bá Medeba. Àwọn ará Amoni náà wá kó àwọn ọmọ ogun wọn jọ láti gbogbo ìlú wọn.

8 Nígbà tí Dafidi gbọ́, ó rán Joabu ati gbogbo àwọn akọni jagunjagun rẹ̀ jáde lọ bá wọn.

9 Àwọn ogun Amoni tò lẹ́sẹẹsẹ siwaju ẹnubodè ìlú wọn, ṣugbọn àwọn ọba tí wọ́n bẹ̀ lọ́wẹ̀ wà lọ́tọ̀ ninu pápá.

10 Nígbà tí Joabu rí i pé àwọn ọ̀tá ti gbógun ti òun níwájú ati lẹ́yìn, ó yan àwọn akọni ninu àwọn ọmọ ogun Israẹli láti dojú kọ àwọn ará Siria.

11 Ó fi àwọn ọmọ ogun yòókù sí abẹ́ Abiṣai, arakunrin rẹ̀, wọ́n sì dojú kọ àwọn ọmọ ogun Amoni.

12 Joabu ní, “Bí àwọn ọmọ ogun Siria bá lágbára jù fún mi, wá ràn mí lọ́wọ́, bí ó bá sì jẹ́ pé àwọn ọmọ ogun Amoni ni wọ́n bá lágbára jù fún ọ, n óo wá ràn ọ́ lọ́wọ́.

13 Ṣe ọkàn rẹ gírí, jẹ́ kí á jà gidigidi fún àwọn eniyan wa, ati fún àwọn ìlú Ọlọrun wa; kí OLUWA ṣe ohun tí ó bá dára lójú rẹ̀.”

14 Joabu ati àwọn ogun Israẹli súnmọ́ àwọn ọmọ ogun Siria láti bá wọn jà, ṣugbọn àwọn ọmọ ogun Siria sá fún wọn.

15 Nígbà tí àwọn ará Amoni rí i pé àwọn ará Siria sá, àwọn náà sá fun Abiṣai, wọn sì wọ ìlú wọn lọ. Joabu bá pada sí Jerusalẹmu.

16 Nígbà tí àwọn ará Siria rí i pé àwọn ará Israẹli ṣẹgun àwọn, wọ́n ranṣẹ lọ pe àwọn ọmọ ogun Siria tí wọ́n wà ni ìkọjá odò Yufurate, wọ́n sì fi wọ́n sí abẹ́ Ṣobaki, balogun Hadadeseri.

17 Nígbà tí Dafidi gbọ́, ó kó gbogbo ọmọ ogun Israẹli jọ, wọ́n rékọjá odò Jọdani, wọ́n lọ dojú kọ ogun Siria, àwọn ọmọ ogun Siria bá bẹ̀rẹ̀ sí bá Dafidi jagun.

18 Àwọn ogun Siria sá níwájú Israẹli. Dafidi pa ẹẹdẹgbaarin (7,000) àwọn tí wọn ń wa kẹ̀kẹ́-ogun ati ọ̀kẹ́ meji (40,000) ọmọ ogun ẹlẹ́sẹ̀, ó sì pa Ṣobaki olórí ogun Siria.

19 Nígbà tí àwọn iranṣẹ Hadadeseri rí i pé Israẹli ti ṣẹgun àwọn, wọ́n bẹ Dafidi, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí sìn ín. Nítorí náà, àwọn ará Siria kò wá ran àwọn ará Amoni lọ́wọ́ mọ́.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24 25 26 27 28 29