Kronika Kinni 13 BM

A Gbé Àpótí Majẹmu kúrò ní Kiriati Jearimu

1 Dafidi jíròrò pẹlu àwọn ọ̀gágun ẹgbẹẹgbẹrun ọmọ ogun ati àwọn ti ọgọọgọrun-un, ati gbogbo àwọn olórí.

2 Lẹ́yìn náà ó sọ fún gbogbo ìjọ Israẹli pé, “Bí ó bá dára lójú yín, tí ó sì jẹ́ ìfẹ́ OLUWA Ọlọrun wa, ẹ jẹ́ kí á ranṣẹ lọ sọ́dọ̀ àwọn eniyan wa tí wọ́n ṣẹ́kù ní ilé Israẹli, ati àwọn alufaa ati àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú tí wọ́n ní pápá oko, kí wọ́n wá darapọ̀ mọ́ wa.

3 Kí á sì lọ sí ibi tí Àpótí Majẹmu Ọlọrun, tí a ti patì láti ayé Saulu wà, kí á gbé e pada wá sọ́dọ̀ wa.”

4 Gbogbo ìjọ eniyan sì gbà bẹ́ẹ̀ nítorí pé ó dára lójú wọn.

5 Nítorí náà Dafidi kó àwọn ọmọ Israẹli jọ láti Ṣihori ní Ijipti títí dé ẹnubodè Hamati láti lọ gbé Àpótí Majẹmu Ọlọrun láti Kiriati Jearimu lọ sí Jerusalẹmu.

6 Dafidi ati gbogbo ọmọ Israẹli lọ sí ìlú Baala, tí à ń pè ní Kiriati Jearimu, ninu ilẹ̀ ẹ̀yà Juda, wọ́n lọ gbé Àpótí Majẹmu tí à ń fi orúkọ OLUWA pè, OLUWA tí ó jókòó, tí ó fi àwọn Kerubu ṣe ìtẹ́.

7 Wọ́n gbé Àpótí Majẹmu náà jáde láti ilé Abinadabu, wọ́n gbé e lé orí kẹ̀kẹ́ titun. Usa ati Ahio sì ń wa kẹ̀kẹ́ náà.

8 Dafidi ati àwọn eniyan ń fi tagbára-tagbára jó níwájú Ọlọrun, pẹlu orin ati àwọn ohun èlò orin: dùùrù, hapu, ìlù, Kimbali ati fèrè.

9 Bí wọ́n ti dé ibi ìpakà Kidoni, àwọn mààlúù tí wọn ń fa kẹ̀kẹ́ náà kọsẹ̀, Usa bá di Àpótí Majẹmu náà mú kí ó má baà ṣubú.

10 Ṣugbọn inú bí Ọlọrun sí Usa, ó sì lù ú pa, nítorí pé ó fi ọwọ́ kan Àpótí Majẹmu, ó sì kú níwájú Ọlọrun.

11 Inú bí Dafidi nítorí pé Ọlọrun lu Usa pa, láti ọjọ́ náà ni a ti ń pe ibẹ̀ ní Peresi Usa títí di òní.

12 Ẹ̀rù Ọlọrun ba Dafidi ní ọjọ́ náà, ó ní, “Báwo ni mo ṣe lè gbé Àpótí Majẹmu Ọlọrun sọ́dọ̀?”

13 Nítorí náà, Dafidi kò gbé Àpótí Majẹmu sọ́dọ̀ ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi, kàkà bẹ́ẹ̀, ó gbé e yà sí ilé Obedi Edomu, ará Giti.

14 Àpótí Majẹmu Ọlọrun náà wà ní ilé Obedi Edomu yìí fún oṣù mẹta, OLUWA sì bukun ilé Obedi Edomu ati gbogbo ohun tí ó ní.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24 25 26 27 28 29