13 ẹ̀yin ọmọ Abrahamu, iranṣẹ rẹ̀,ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
14 Òun ni OLUWA Ọlọrun wa,ìdájọ́ rẹ̀ ká gbogbo ayé.
15 Kò ní í gbàgbé majẹmu rẹ̀ títí lae,àní àwọn ohun tí ó ti pa láṣẹ láti ṣe fún ẹgbẹẹgbẹrun ìran,
16 majẹmu tí ó bá Abrahamu dá,ìlérí tí ó ti ṣe fún Isaaki,
17 tí ó sì ti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pẹlu Jakọbu,gẹ́gẹ́ bíi majẹmu ohun tí yóo wà títí lae,
18 ó ní, “Ẹ̀yin ni n óo fún ní ilẹ̀ Kenaani,bí ohun ìní yín, tí ẹ óo jogún.”
19 Nígbà tí wọn kò tíì pọ̀ pupọ,tí wọn kò sì jẹ́ nǹkan,tí wọ́n jẹ́ àjèjì níbẹ̀,