19 Nígbà tí wọn kò tíì pọ̀ pupọ,tí wọn kò sì jẹ́ nǹkan,tí wọ́n jẹ́ àjèjì níbẹ̀,
20 tí wọn ń lọ káàkiri láti orílẹ̀-èdè kan dé ekeji,láti ìjọba kan sí òmíràn,
21 kò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ni wọ́n lára,ó bá àwọn ọba wí nítorí wọn.
22 Ó ní, “Ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi,ẹ má sì pa àwọn wolii mi lára!”
23 Ẹ kọrin sí OLUWA, gbogbo ayé!Ẹ máa kéde ìgbàlà rẹ̀ lojoojumọ.
24 Ẹ kéde ògo rẹ̀ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè,ẹ polongo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrin àwọn eniyan!
25 OLUWA tóbi, ìyìn tọ́ sí i lọpọlọpọó sì yẹ kí á bọ̀wọ̀ fún un ju gbogbo àwọn oriṣa lọ.