7 Ní ọjọ́ náà, àṣẹ àkọ́kọ́ tí Dafidi pa ni pé kí Asafu ati àwọn arakunrin rẹ̀ máa kọ orin ìyìn sí OLUWA.
8 Ẹ fi ọpẹ́ fún OLUWA, ẹ képe orúkọ rẹ̀,ẹ kéde ohun tí ó ti ṣe fún àwọn orílẹ̀-èdè.
9 Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn sí i,ẹ sọ nípa àwọn ohun ìyanu tí ó ṣe!
10 Ẹ máa fi orúkọ rẹ̀ ṣògo,kí ọkàn àwọn tí wọn ń sin OLUWA kún fún ayọ̀.
11 OLUWA ni kí ẹ máa tọ̀ lọ fún ìrànlọ́wọ́,Ẹ máa sìn ín nígbà gbogbo.
12 Ẹ ranti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀,gbogbo nǹkan ìyanu tí ó ṣe, ati gbogbo ìdájọ́ rẹ̀,
13 ẹ̀yin ọmọ Abrahamu, iranṣẹ rẹ̀,ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.