Kronika Kinni 28:15-21 BM

15 ti ìwọ̀n àwọn ọ̀pá fìtílà wúrà ati àwọn fìtílà wọn, ti ìwọ̀n fadaka fún ọ̀pá fìtílà kan ati àwọn fìtílà wọn, gẹ́gẹ́ bí ìlò olukuluku wọn ninu ìsìn.

16 Ètò ìwọ̀n wúrà fún tabili àkàrà ìfihàn kọ̀ọ̀kan ati ìwọ̀n fadaka fún tabili fadaka kọ̀ọ̀kan,

17 ìwọ̀n ojúlówó wúrà fún àwọn àmúga tí a fi ń mú ẹran, àwọn agbada, àwọn ife, àwọn abọ́ wúrà ati ti ìwọ̀n abọ́ fadaka kọ̀ọ̀kan,

18 ìwọ̀n pẹpẹ turari tí a fi wúrà yíyọ́ ṣe ati ohun tí ó ní lọ́kàn nípa àwọn kẹ̀kẹ́ wúrà àwọn Kerubu tí wọ́n na ìyẹ́ wọn bo Àpótí Majẹmu OLUWA.

19 Gbogbo nǹkan wọnyi ni ó kọ sílẹ̀ fínnífínní gẹ́gẹ́ bí ìlànà láti ọ̀dọ̀ OLUWA nípa iṣẹ́ inú tẹmpili; ó ní gbogbo rẹ̀ ni wọ́n sì gbọdọ̀ ṣe gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ náà.

20 Dafidi bá sọ fún Solomoni, ọmọ rẹ̀ pé, “Múra gírí, mú ọkàn le, kí o sì ṣe bí mo ti wí. Má bẹ̀rù, má sì jẹ́ kí ọkàn rẹ rẹ̀wẹ̀sì; nítorí OLUWA Ọlọrun, àní Ọlọrun mi, wà pẹlu rẹ. Kò ní já ọ kulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò ní kọ̀ ọ́ sílẹ̀, títí tí iṣẹ́ ilé OLUWA yóo fi parí.

21 Gbogbo ètò iṣẹ́ ati pípín àwọn alufaa ati àwọn ọmọ Lefi ninu tẹmpili ni a ti ṣe fínnífínní. Àwọn tí wọ́n mọ oríṣìíríṣìí iṣẹ́ yóo wà pẹlu rẹ, bákan náà, àwọn olórí ati gbogbo eniyan Israẹli yóo wà lábẹ́ àṣẹ rẹ.”