Kronika Kinni 28:2-8 BM

2 Dafidi bá dìde dúró, ó ní, “Ẹ gbọ́ mi, ẹ̀yin ará mi ati eniyan mi, mo ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé ìsinmi fún Àpótí Majẹmu OLUWA, ati fún àpótí ìtìsẹ̀ Ọlọrun wa; mo ti tọ́jú gbogbo nǹkan sílẹ̀, mo sì ti múra tán.

3 Ṣugbọn, Ọlọrun sọ fún mi pé, kì í ṣe èmi ni n óo kọ́ ilé fún òun, nítorí pé jagunjagun ni mí, mo sì ti ta ẹ̀jẹ̀ pupọ sílẹ̀.

4 Sibẹsibẹ OLUWA Ọlọrun Israẹli yàn mí ninu ilé baba mi láti jọba lórí Israẹli títí lae; nítorí pé ó yan ẹ̀yà Juda láti ṣe aṣaaju Israẹli. Ninu ẹ̀yà Juda, ó yan ilé baba mi, láàrin àwọn ọmọ baba mi, ó ní inú dídùn sí mi, ó fi mí jọba lórí gbogbo Israẹli.

5 OLUWA fún mi ní ọmọ pupọ, ṣugbọn ninu gbogbo wọn, ó yan Solomoni láti jọba lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀ lórí Israẹli.

6 “OLUWA sọ fún mi pé, ‘Solomoni, ọmọ rẹ ni yóo kọ́ ilé mi ati àgbàlá mi, nítorí mo ti yàn án láti jẹ́ ọmọ mi, èmi yóo sì jẹ́ baba fún un.

7 N óo fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ títí lae, bí ó bá ti pinnu láti máa pa òfin ati ìlànà mi mọ́, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń ṣe nisinsinyii.’

8 “Nítorí náà, lójú gbogbo ọmọ Israẹli, lójú ìjọ eniyan OLUWA, ati ní etígbọ̀ọ́ Ọlọrun wa, mò ń kìlọ̀ fun yín pé kí ẹ máa pa gbogbo òfin OLUWA Ọlọrun yín mọ́, kí ẹ̀yin ati arọmọdọmọ yín baà lè máa gbé ilẹ̀ yìí títí lae.